Sáàmù 17:1-15

  • Àdúrà ààbò

    • “O ti ṣàyẹ̀wò ọkàn mi” (3)

    • “Òjìji ìyẹ́ apá rẹ” (8)

Àdúrà Dáfídì. 17  Jèhófà, gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi fún ìdájọ́ òdodo;Fiyè sí igbe mi fún ìrànlọ́wọ́;Fetí sí àdúrà tí mo gbà láìṣẹ̀tàn.+   Kí o ṣe ìpinnu tí ó tọ́ nítorí mi;+Kí ojú rẹ rí ohun tí ó tọ́.   O ti ṣàyẹ̀wò ọkàn mi, o ti bẹ̀ mí wò ní òru;+O ti yọ́ mi mọ́;+Wàá rí i pé mi ò ní èrò ibi kankan lọ́kàn,Ẹnu mi kò sì dẹ́ṣẹ̀.   Ohunkóhun tí àwọn èèyàn ì báà máa ṣe,Nítorí ọ̀rọ̀ rẹ, mo yẹra fún ọ̀nà àwọn ọlọ́ṣà.+   Má ṣe jẹ́ kí ìṣísẹ̀ mi kúrò ní ọ̀nà rẹKí n má bàa kọsẹ̀.+   Ọlọ́run, mò ń ké pè ọ́, torí mo mọ̀ pé wàá dá mi lóhùn.+ Tẹ́tí sí mi.* Gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.+   Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ hàn lọ́nà àgbàyanu,+Ìwọ Olùgbàlà àwọn tó ń wá ààbò ní ọwọ́ ọ̀tún rẹKí ọwọ́ àwọn tó ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọ má bàa tẹ̀ wọ́n.   Dáàbò bò mí bí ọmọlójú rẹ;+Fi mí pa mọ́ sábẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ.+   Dáàbò bò mí lọ́wọ́ àwọn ẹni burúkú tó ń gbéjà kò mí. Lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá alénimádẹ̀yìn* tí wọ́n yí mi ká.+ 10  Wọ́n ti yigbì;*Wọ́n ń fi ẹnu wọn sọ̀rọ̀ ìgbéraga; 11  Ní báyìí, wọ́n ti ká wa mọ́;+Wọ́n ń wá ọ̀nà tí wọ́n á fi gbé wa ṣubú.* 12  Ó dà bíi kìnnìún tó fẹ́ fa ẹran ya,Bí ọmọ kìnnìún tó lúgọ síbi ìkọ̀kọ̀. 13  Dìde Jèhófà, kí o kò ó lójú+ kí o sì mú un balẹ̀;Fi idà rẹ gbà mí* lọ́wọ́ ẹni burúkú; 14  Jèhófà, fi ọwọ́ rẹ gbà mí sílẹ̀,Lọ́wọ́ àwọn èèyàn ayé* yìí, àwọn tí ìpín wọn jẹ́ ti ayé yìí,+Àwọn tí o fún ní àwọn ohun rere tí o ti pèsè,+Àwọn tí wọ́n fi ogún sílẹ̀ fún ọmọ púpọ̀. 15  Àmọ́ ní tèmi, màá rí ojú rẹ nínú òdodo;Ó tẹ́ mi lọ́rùn láti máa jí rí ọ.*+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “Bẹ̀rẹ̀ kí o sì fetí sí mi.”
Tàbí “àwọn ọ̀tá tó ń wá ọkàn mi.”
Tàbí “Ọ̀rá wọn ti bò wọ́n lára.”
Tàbí “tì wá ṣubú.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Tàbí “ètò àwọn nǹkan.”
Tàbí “láti rí ìrísí rẹ.”