Sáàmù 143:1-12

  • Mò ń wá Ọlọ́run bí ilẹ̀ gbígbẹ ṣe ń wá òjò

    • ‘Mò ń ronú lórí àwọn iṣẹ́ rẹ’ (5)

    • “Kọ́ mi láti máa ṣe ìfẹ́ rẹ” (10)

    • ‘Kí ẹ̀mí dáradára rẹ máa darí mi’ (10)

Orin Dáfídì. 143  Jèhófà, gbọ́ àdúrà mi;+Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi fún ìrànlọ́wọ́. Dá mi lóhùn nínú òtítọ́ rẹ àti òdodo rẹ.  Má ṣe bá ìránṣẹ́ rẹ ṣẹjọ́,Nítorí kò sí alààyè kankan tó lè jẹ́ olódodo níwájú rẹ.+  Nítorí ọ̀tá ń lépa mi;*Ó ti tẹ ẹ̀mí mi mọ́lẹ̀. Ó ti mú kí n máa gbé inú òkùnkùn bí àwọn tó ti kú tipẹ́tipẹ́.  Àárẹ̀ mú ẹ̀mí mi;*+Ọkàn mi kú tipiri nínú mi.+  Mo rántí àwọn ọjọ́ àtijọ́;Mo ṣe àṣàrò lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ;+Ó ń yá mi lára láti máa ronú lórí* iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.  Mo tẹ́ ọwọ́ mi sí ọ;* ń wá ọ bí ilẹ̀ tó gbẹ táútáú ṣe ń wá òjò.+ (Sélà)  Jọ̀ọ́ Jèhófà, tètè dá mi lóhùn;+Agbára* mi ti tán.+ Má fi ojú rẹ pa mọ́ fún mi,+Kí n má bàa dà bí àwọn tó ń lọ sínú kòtò.*+  Ní àárọ̀, jẹ́ kí n gbọ́ nípa ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,Nítorí mo gbẹ́kẹ̀ lé ọ. Jẹ́ kí n mọ ọ̀nà tó yẹ kí n máa rìn,+Nítorí ìwọ ni mo yíjú sí.*  Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi, Jèhófà. Ààbò rẹ ni mò ń wá.+ 10  Kọ́ mi láti máa ṣe ìfẹ́ rẹ,+Nítorí ìwọ ni Ọlọ́run mi. Ẹ̀mí rẹ dára;Kí ó máa darí mi ní ilẹ̀ tó tẹ́jú.* 11  Jèhófà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí n máa wà láàyè nítorí orúkọ rẹ. Gbà mí* nínú wàhálà nítorí òdodo rẹ.+ 12  Pa àwọn ọ̀tá mi rẹ́*+ nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀;Pa gbogbo àwọn tó ń halẹ̀ mọ́ mi* run,+Nítorí ìránṣẹ́ rẹ ni mí.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ọkàn mi.”
Tàbí “Mi ò lágbára mọ́.”
Tàbí “kẹ́kọ̀ọ́ nípa.”
Tàbí “Ọkàn mi.”
Tàbí “sàréè.”
Ní Héb., “Ẹ̀mí.”
Tàbí “ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.”
Tàbí “ilẹ̀ adúróṣinṣin.”
Tàbí “Gba ọkàn mi.”
Ní Héb., “lẹ́nu mọ́.”
Tàbí “ọkàn mi.”