Sáàmù 136:1-26
136 Ẹ fi ọpẹ́ fún Jèhófà, nítorí ó jẹ́ ẹni rere;+Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.+
2 Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run àwọn ọlọ́run,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
3 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa àwọn olúwa,Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
4 Òun nìkan ló ń ṣe àwọn ohun àgbàyanu,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.+
5 Ó fi ọgbọ́n* dá àwọn ọ̀run,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
6 Ó tẹ́ ayé sórí omi,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
7 Ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
8 Oòrùn láti máa jọba lórí ọ̀sán,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
9 Òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ láti máa jọba lórí òru,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
10 Ó pa àwọn àkọ́bí Íjíbítì,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
11 Ó mú Ísírẹ́lì jáde kúrò láàárín wọn,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
12 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára+ àti apá tó nà jáde,Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
13 Ó pín Òkun Pupa sí méjì,*+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
14 Ó mú kí Ísírẹ́lì gba àárín rẹ̀ kọjá,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
15 Ó gbọn Fáráò àti àwọn ọmọ ogun rẹ̀ sínú Òkun Pupa,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
16 Ó mú àwọn èèyàn rẹ̀ gba inú aginjù kọjá,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
17 Ó pa àwọn ọba ńlá,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
18 Ó pa àwọn ọba alágbára,Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
19 Síhónì+ ọba àwọn Ámórì,Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé
20 Àti Ógù+ ọba Báṣánì,Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
21 Ó fi ilẹ̀ wọn ṣe ogún,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
22 Ó fi ṣe ogún fún Ísírẹ́lì ìránṣẹ́ rẹ̀,Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
23 Ó rántí wa nígbà tí wọ́n rẹ̀ wá sílẹ̀,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.+
24 Ó ń gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
25 Ó ń fún gbogbo ohun alààyè* ní oúnjẹ,+Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.
26 Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run ọ̀run,Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.

