Sáàmù 135:1-21

  • Ẹ yin Jáà nítorí ó tóbi

    • Iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu lórí Íjíbítì (8, 9)

    • “Orúkọ rẹ wà títí láé” (13)

    • Òrìṣà aláìlẹ́mìí (15-18)

135  Ẹ yin Jáà!* Ẹ yin orúkọ Jèhófà;Ẹ mú ìyìn wá, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Jèhófà,+  Ẹ̀yin tó ń ṣiṣẹ́ nínú ilé Jèhófà,Nínú àwọn àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.+  Ẹ yin Jáà, nítorí Jèhófà jẹ́ ẹni rere.+ Ẹ kọ orin ìyìn* sí orúkọ rẹ̀, nítorí ó dára.  Jáà ti yan Jékọ́bù fún ara rẹ̀,Ó ti yan Ísírẹ́lì ṣe ohun ìní rẹ̀ pàtàkì.*+  Mo mọ̀ dáadáa pé Jèhófà tóbi;Olúwa wa ju gbogbo ọlọ́run yòókù lọ.+  Jèhófà ń ṣe gbogbo ohun tó bá fẹ́+Ní ọ̀run àti ní ayé, nínú òkun àti nínú gbogbo ibú omi.  Ó ń mú kí ìkùukùu* ròkè láti ìkángun ayé;Ó ń ṣe mànàmáná* fún òjò;Ó ń mú ẹ̀fúùfù jáde látinú àwọn ilé ìṣúra rẹ̀.+  Ó pa àwọn àkọ́bí Íjíbítì,Àti èèyàn àti ẹranko.+  Ó rán àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sáàárín rẹ, ìwọ Íjíbítì,+Sí Fáráò àti sí gbogbo ìránṣẹ́ rẹ̀.+ 10  Ó pa ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè+ run,Ó sì pa àwọn ọba alágbára+ 11  —Síhónì ọba àwọn Ámórì,+Ógù ọba Báṣánì+Àti gbogbo àwọn ìjọba Kénáánì. 12  Ó fi ilẹ̀ wọn ṣe ogún,Ó fi ṣe ogún fún Ísírẹ́lì, àwọn èèyàn rẹ̀.+ 13  Jèhófà, orúkọ rẹ wà títí láé. Jèhófà, òkìkí rẹ yóò máa kàn* láti ìran dé ìran.+ 14  Nítorí Jèhófà yóò gbèjà àwọn èèyàn rẹ̀,*+Yóò sì ṣàánú* àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.+ 15  Àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè jẹ́ fàdákà àti wúrà,Iṣẹ́ ọwọ́ èèyàn.+ 16  Wọ́n ní ẹnu, àmọ́ wọn ò lè sọ̀rọ̀;+Wọ́n ní ojú, àmọ́ wọn ò lè ríran; 17  Wọ́n ní etí, àmọ́ wọn ò lè gbọ́ràn. Kò sí èémí kankan ní ẹnu wọn.+ 18  Àwọn tó ń ṣe wọ́n yóò dà bíi wọn gẹ́lẹ́,+Bẹ́ẹ̀ ló sì ṣe máa rí fún gbogbo àwọn tó gbẹ́kẹ̀ lé wọn.+ 19  Ilé Ísírẹ́lì, ẹ yin Jèhófà. Ilé Áárónì, ẹ yin Jèhófà. 20  Ilé Léfì, ẹ yin Jèhófà.+ Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Jèhófà, ẹ yin Jèhófà. 21  Ìyìn ni fún Jèhófà láti Síónì,+Ẹni tó ń gbé ní Jerúsálẹ́mù.+ Ẹ yin Jáà!+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “Halelúyà!” “Jáà” ni ìkékúrú Jèhófà.
Tàbí “kọrin.”
Tàbí “ohun ìní rẹ̀ tó ṣeyebíye.”
Tàbí kó jẹ́, “ọ̀ṣọ̀ọ̀rọ̀.”
Tàbí “oruku.”
Tàbí “orúkọ rẹ yóò wà.” Ní Héb., “ìrántí.”
Tàbí “gba ẹjọ́ àwọn èèyàn rẹ̀ rò.”
Tàbí “kẹ́dùn nítorí.”