Sáàmù 132:1-18
Orin Ìgòkè.
132 Jèhófà, jọ̀wọ́ rántí DáfídìÀti gbogbo ìyà tó jẹ;+
2 Bó ṣe búra fún Jèhófà,Bó ṣe jẹ́jẹ̀ẹ́ fún Alágbára Jékọ́bù pé:+
3 “Mi ò ní wọnú àgọ́ mi, àní ilé mi.+
Mi ò ní dùbúlẹ̀ lórí àga tìmùtìmù mi, àní ibùsùn mi;
4 Mi ò ní jẹ́ kí oorun kun ojú mi,Mi ò sì ní jẹ́ kí ìpéǹpéjú mi tòògbé
5 Títí màá fi rí àyè kan fún Jèhófà,Ibùgbé tó dáa* fún Alágbára Jékọ́bù.”+
6 Wò ó! A gbọ́ nípa rẹ̀ ní Éfúrátà;+A rí i nínú igbó kìjikìji.+
7 Ẹ jẹ́ ká wá sínú ibùgbé rẹ̀;*+Ká forí balẹ̀ níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀.+
8 Dìde, Jèhófà, wá sí ibi ìsinmi rẹ,+Ìwọ àti Àpótí agbára rẹ.+
9 Kí àwọn àlùfáà rẹ gbé òdodo wọ̀,Kí àwọn ẹni ìdúróṣinṣin rẹ sì máa kígbe ayọ̀.
10 Nítorí Dáfídì ìránṣẹ́ rẹ,Má ṣe kọ ẹni àmì òróró rẹ sílẹ̀.*+
11 Jèhófà ti búra fún Dáfídì,Ó dájú pé kò ní ṣàìmú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ pé:
“Ọ̀kan lára ọmọ* rẹNi màá gbé gorí ìtẹ́ rẹ.+
12 Tí àwọn ọmọ rẹ bá pa májẹ̀mú mi mọ́Àti àwọn ìránnilétí mi tí mo kọ́ wọn,+Àwọn ọmọ tiwọn náàYóò jókòó sórí ìtẹ́ rẹ títí láé.”+
13 Nítorí Jèhófà ti yan Síónì;+Ó fẹ́ kó jẹ́ ibùgbé rẹ̀, ó ní:+
14 “Ibi ìsinmi mi títí láé nìyí;Ibí ni màá máa gbé,+ nítorí ohun tí mo fẹ́ nìyẹn.
15 Màá fi ọ̀pọ̀ oúnjẹ kún ibẹ̀;Màá fi oúnjẹ tẹ́ àwọn aláìní ibẹ̀ lọ́rùn.+
16 Màá gbé ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀,+Àwọn adúróṣinṣin rẹ̀ yóò sì kígbe ayọ̀.+
17 Màá mú kí agbára Dáfídì pọ̀ sí i* níbẹ̀.
Mo ti ṣètò fìtílà fún ẹni àmì òróró mi.+
18 Màá gbé ìtìjú wọ àwọn ọ̀tá rẹ̀,Àmọ́ adé* orí rẹ̀ yóò máa gbilẹ̀.”+

