Sáàmù 130:1-8
Orin Ìgòkè.
130 Láti inú ibú ni mo ti ké pè ọ́, Jèhófà.+
2 Jèhófà, gbọ́ ohùn mi.
Kí etí rẹ ṣí sí ẹ̀bẹ̀ mi fún ìrànlọ́wọ́.
3 Jáà,* tó bá jẹ́ pé àṣìṣe lò ń wò,*Jèhófà, ta ló lè dúró?+
4 Nítorí ìdáríjì tòótọ́ wà lọ́dọ̀ rẹ,+Kí a lè máa bọ̀wọ̀ fún ọ.*+
5 Mo gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà, gbogbo ara* mi gbẹ́kẹ̀ lé e;Mò ń dúró de ọ̀rọ̀ rẹ̀.
6 Mò* ń retí Jèhófà,+Ju bí àwọn olùṣọ́ ṣe ń retí pé kí ilẹ̀ mọ́,+Àní, ju bí àwọn olùṣọ́ ṣe ń retí pé kí ilẹ̀ mọ́.
7 Kí Ísírẹ́lì máa dúró de Jèhófà,Nítorí ìfẹ́ Jèhófà kì í yẹ̀,+Ó sì ní agbára ńlá tó lè fi rani pa dà.
8 Yóò ra Ísírẹ́lì pa dà nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

