Sáàmù 126:1-6

  • Ayọ̀ sọ nígbà tí Ọlọ́run kó àwọn èèyàn Síónì pa dà

    • “Jèhófà ti ṣe àwọn ohun ńlá” (3)

    • Ẹkún di ayọ̀ (5, 6)

Orin Ìgòkè. 126  Nígbà tí Jèhófà kó àwọn èèyàn Síónì tó wà lóko ẹrú pa dà,+A rò pé à ń lá àlá ni.   Ní àkókò yẹn, ẹ̀rín kún ẹnu wa,Ahọ́n wa sì ń kígbe ayọ̀.+ Ní àkókò yẹn, wọ́n ń sọ láàárín àwọn orílẹ̀-èdè pé: “Jèhófà ti ṣe àwọn ohun ńlá fún wọn.”+   Jèhófà ti ṣe àwọn ohun ńlá fún wa,+Ayọ̀ wa sì kún.   Jèhófà, jọ̀wọ́ kó* àwọn èèyàn wa tó wà lóko ẹrú pa dà,Bí ìṣàn omi tó wà ní Négébù.*   Àwọn tó ń fi omijé fúnrúgbìnYóò fi igbe ayọ̀ kórè.   Ẹni tó ń jáde, bó tilẹ̀ ń sunkún,Tó gbé àpò irúgbìn rẹ̀ dání,Ó dájú pé ó máa pa dà pẹ̀lú igbe ayọ̀,+Bó ṣe ń gbé àwọn ìtí rẹ̀ wọlé.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “mú.”
Tàbí “Bí àwọn àfonífojì tó wà ní gúúsù.”