Sáàmù 125:1-5

  • Jèhófà ń dáàbò bo àwọn èèyàn rẹ̀

    • “Bí àwọn òkè ṣe yí Jerúsálẹ́mù ká” (2)

    • “Kí àlàáfíà wà ní Ísírẹ́lì” (5)

Orin Ìgòkè. 125  Àwọn tó gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà+Dà bí Òkè Síónì, tí kò ṣeé mì,Àmọ́ tí ó wà títí láé.+   Bí àwọn òkè ṣe yí Jerúsálẹ́mù ká,+Bẹ́ẹ̀ ni Jèhófà yí àwọn èèyàn rẹ̀ ká+Láti ìsinsìnyí lọ àti títí láé.   Ọ̀pá àṣẹ ìwà burúkú kò ní máa wà lórí ilẹ̀ tí a pín fún àwọn olódodo,+Kí àwọn olódodo má bàa bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe* ohun tí kò tọ́.+   Jèhófà, ṣe rere sí àwọn ẹni rere,+Sí àwọn tí ọkàn wọn dúró ṣinṣin.+   Ní ti àwọn tó yà sí ọ̀nà àìtọ́,Jèhófà yóò mú wọn kúrò pẹ̀lú àwọn aṣebi.+ Kí àlàáfíà wà ní Ísírẹ́lì.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “rawọ́ lé.”