Sáàmù 124:1-8

  • “Ká ní Jèhófà ò wà pẹ̀lú wa ni”

    • Bọ́ nínú pańpẹ́ tó ṣẹ́ (7)

    • ‘Orúkọ Jèhófà ni ìrànlọ́wọ́ wa’ (8)

Orin Ìgòkè. Ti Dáfídì. 124  “Ká ní Jèhófà ò wà pẹ̀lú wa ni”+—Kí Ísírẹ́lì sọ pé—  “Ká ní Jèhófà ò wà pẹ̀lú wa ni+Nígbà tí àwọn èèyàn dìde láti bá wa jà,+  Wọn ì bá ti gbé wa mì láàyè+Nígbà tí inú wọn ń ru sí wa.+  Omi ì bá ti gbé wa lọ,Ọ̀gbàrá ì bá ti ṣàn kọjá lórí wa.*+  Omi tó ń ru gùdù ì bá ti bò wá* mọ́lẹ̀.  Ìyìn ni fún Jèhófà,Torí kò fi wá ṣe ẹran ìjẹ fún eyín wọn.  A* dà bí ẹyẹ tó bọ́Nínú pańpẹ́ ọdẹ;+Pańpẹ́ náà ṣẹ́,A sì bọ́.+  Ìrànlọ́wọ́ wa wà nínú orúkọ Jèhófà,+Aṣẹ̀dá ọ̀run àti ayé.”

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ọkàn wa.”
Tàbí “bo ọkàn wa.”
Tàbí “Ọkàn wa.”