Sáàmù 120:1-7

  • Àjèjì tó ń fẹ́ àlàáfíà

    • ‘Gbà mí lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn’ (2)

    • “Àlàáfíà ni èmi ń fẹ́” (7)

Orin Ìgòkè.* 120  Mo ké pe Jèhófà nínú wàhálà mi,+Ó sì dá mi lóhùn.+   Jèhófà, gbà mí* lọ́wọ́ ètè tó ń parọ́Àti lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn.   Ṣé o mọ ohun tí Ó máa ṣe sí ọ, ṣé o mọ ìyà tí Ó máa fi jẹ ọ́,*Ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn?+   Yóò lo àwọn ọfà mímú+ jagunjagunÀti ẹyin iná+ àwọn igi wíwẹ́.   Mo gbé, nítorí mo jẹ́ àjèjì ní Méṣékì!+ Mò ń gbé láàárín àwọn àgọ́ Kídárì.+   Mo* ti ń gbé tipẹ́tipẹ́Pẹ̀lú àwọn tó kórìíra àlàáfíà.+   Àlàáfíà ni èmi ń fẹ́, àmọ́ nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀,Ogun ni wọ́n ń fẹ́.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “gba ọkàn mi.”
Ní Héb., “kí ni Òun yóò sì fi kún un fún ọ?”
Tàbí “Ọkàn mi.”