Sáàmù 115:1-18

  • Ọlọ́run nìkan ni ògo yẹ

    • Àwọn òrìṣà aláìlẹ́mìí (4-8)

    • Ọlọ́run fi ayé fún àwọn èèyàn (16)

    • “Àwọn òkú kì í yin Jáà” (17)

115  Kì í ṣe àwa, Jèhófà, kì í ṣe àwa,*Àmọ́ orúkọ rẹ ni ògo yẹ+Nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ àti òtítọ́ rẹ.+   Ṣé ó yẹ kí àwọn orílẹ̀-èdè sọ pé: “Ọlọ́run wọn dà?”+   Ọlọ́run wa wà ní ọ̀run;Ó ń ṣe ohun tí ó bá fẹ́.   Àwọn òrìṣà wọn jẹ́ fàdákà àti wúrà,Iṣẹ́ ọwọ́ èèyàn.+   Wọ́n ní ẹnu, àmọ́ wọn ò lè sọ̀rọ̀;+Wọ́n ní ojú, àmọ́ wọn ò lè ríran;   Wọ́n ní etí, àmọ́ wọn ò lè gbọ́ràn;Wọ́n ní imú, àmọ́ wọn ò lè gbóòórùn;   Wọ́n ní ọwọ́, àmọ́ wọn ò lè fọwọ́ ba nǹkan;Wọ́n ní ẹsẹ̀, àmọ́ wọn ò lè rìn;+Wọn ò lè mú ìró kankan jáde láti ọ̀fun wọn.+   Àwọn tó ń ṣe wọ́n yóò dà bíi wọn gẹ́lẹ́,+Bẹ́ẹ̀ ló sì ṣe máa rí fún gbogbo àwọn tó gbẹ́kẹ̀ lé wọn.+   Ísírẹ́lì, gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà+—Òun ni olùrànlọ́wọ́ wọn àti apata wọn.+ 10  Ilé Áárónì,+ ẹ gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà—Òun ni olùrànlọ́wọ́ wọn àti apata wọn. 11  Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Jèhófà, ẹ gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà+—Òun ni olùrànlọ́wọ́ wọn àti apata wọn.+ 12  Jèhófà ń rántí wa, á sì bù kún wa;Á bù kún ilé Ísírẹ́lì;+Á bù kún ilé Áárónì. 13  Á bù kún àwọn tó bẹ̀rù Jèhófà,Àti ẹni kékeré àti ẹni ńlá. 14  Jèhófà máa mú kí ẹ pọ̀ sí i,Ẹ̀yin àti àwọn ọmọ* yín.+ 15  Kí Jèhófà bù kún yín,+Aṣẹ̀dá ọ̀run àti ayé.+ 16  Ní ti ọ̀run, ti Jèhófà ni,+Àmọ́ ayé ni ó fún àwọn ọmọ èèyàn.+ 17  Àwọn òkú kì í yin Jáà;+Bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni tó sọ̀ kalẹ̀ lọ sínú ìdákẹ́jẹ́ẹ́ ikú.*+ 18  Àmọ́ a ó máa yin JáàLáti ìsinsìnyí lọ àti títí láé. Ẹ yin Jáà!*

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “Kò sóhun tó jẹ́ tiwa, Jèhófà, kò sóhun tó jẹ́ tiwa.”
Ní Héb., “àwọn ọmọkùnrin.”
Ní Héb., “sínú ìdákẹ́jẹ́ẹ́.”
Tàbí “Halelúyà!” “Jáà” ni ìkékúrú Jèhófà.