Sáàmù 110:1-7
Ti Dáfídì. Orin.
110 Jèhófà sọ fún Olúwa mi pé:
“Jókòó sí ọwọ́ ọ̀tún mi+Títí màá fi fi àwọn ọ̀tá rẹ ṣe àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.”+
2 Jèhófà yóò na ọ̀pá agbára rẹ jáde láti Síónì, yóò sọ pé:
“Máa ṣẹ́gun lọ láàárín àwọn ọ̀tá rẹ.”+
3 Àwọn èèyàn rẹ máa yọ̀ǹda ara wọn tinútinú ní ọjọ́ ìjáde ogun rẹ.*
Nínú ọlá ńlá ìjẹ́mímọ́, láti ibi tí ọ̀yẹ̀ ti ń là,*O ní àwùjọ àwọn ọ̀dọ́ tí wọ́n rí bí ìrì tó ń sẹ̀.
4 Jèhófà ti búra, kò sì ní pèrò dà,* ó ní:
“Ìwọ jẹ́ àlùfáà títí láé+Ní ọ̀nà ti Melikisédékì!”+
5 Jèhófà yóò wà ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ;+Yóò fọ́ àwọn ọba túútúú ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.+
6 Yóò mú ìdájọ́ ṣẹ lórí* àwọn orílẹ̀-èdè;+Yóò fi òkú kún ilẹ̀ náà.+
Yóò fọ́ aṣáájú* ilẹ̀ fífẹ̀* túútúú.
7 Yóò* mu omi odò tó wà lójú ọ̀nà,Yóò sì gbé orí rẹ̀ sókè.

