Sáàmù 106:1-48

  • Ísírẹ́lì kò moore

    • Kò pẹ́ tí wọ́n fi gbàgbé àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run (13)

    • Wọ́n gbé ògo tó yẹ Ọlọ́run fún ère akọ màlúù (19, 20)

    • Wọn ò nígbàgbọ́ nínú ìlérí Ọlọ́run (24)

    • Wọ́n dara pọ̀ mọ́ àwọn tó ń sin Báálì (28)

    • Wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rúbọ sí àwọn ẹ̀mí èṣù (37)

106  Ẹ yin Jáà!* Ẹ fi ọpẹ́ fún Jèhófà, nítorí ó jẹ́ ẹni rere;+Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé.+   Ta ló lè kéde gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Jèhófà ṣeTàbí tó lè kéde gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ tó yẹ fún ìyìn?+   Aláyọ̀ ni àwọn tó ń ṣe ohun tó bá ẹ̀tọ́ mu,Àwọn tó ń ṣe ohun tí ó tọ́ nígbà gbogbo.+   Jèhófà, rántí mi nígbà tí o bá ń ṣojú rere sí* àwọn èèyàn rẹ.+ Fi àwọn iṣẹ́ ìgbàlà rẹ tọ́jú mi,   Kí n lè gbádùn oore tí ò ń ṣe fún àwọn àyànfẹ́ rẹ,+Kí n lè máa bá orílẹ̀-èdè rẹ yọ̀,Kí n lè máa ṣògo bí mo ṣe ń yìn ọ́* pẹ̀lú ogún rẹ.   A ti dẹ́ṣẹ̀ bí àwọn baba ńlá wa;+A ti ṣe ohun tí kò dáa; a ti hùwà burúkú.+   Àwọn baba ńlá wa ní Íjíbítì kò mọyì* àwọn iṣẹ́ àgbàyanu rẹ. Wọn ò rántí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ tó pọ̀ gidigidi,Wọ́n ṣọ̀tẹ̀ ní òkun, létí Òkun Pupa.+   Àmọ́, ó gbà wọ́n sílẹ̀ nítorí orúkọ rẹ̀,+Kí wọ́n lè mọ bí agbára rẹ̀ ṣe pọ̀ tó.+   Ó bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ;Ó mú wọn gba ìsàlẹ̀ rẹ̀ bí ẹni gba aṣálẹ̀* kọjá;+ 10  Ó gbà wọ́n lọ́wọ́ elénìní,+Ó sì gbà wọ́n pa dà lọ́wọ́ ọ̀tá.+ 11  Omi bo àwọn elénìní wọn;Kò sí ìkankan lára wọn tó yè bọ́.*+ 12  Nígbà náà, wọ́n ní ìgbàgbọ́ nínú ìlérí rẹ̀;+Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í kọrin yìn ín.+ 13  Àmọ́ kò pẹ́ tí wọ́n fi gbàgbé ohun tó ṣe;+Wọn ò dúró de ìmọ̀ràn rẹ̀. 14  Wọ́n jẹ́ kí ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ gbà wọ́n lọ́kàn ní aginjù;+Wọ́n dán Ọlọ́run wò ní aṣálẹ̀.+ 15  Ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè,Àmọ́ lẹ́yìn náà, ó fi àrùn kọ lù wọ́n, wọ́n* sì rù hangogo.+ 16  Ní ibùdó, wọ́n jowú MósèÀti Áárónì,+ ẹni mímọ́ Jèhófà.+ 17  Ni ilẹ̀ bá lanu, ó gbé Dátánì mì,Ó sì bo àwọn tó kóra jọ sọ́dọ̀ Ábírámù.+ 18  Iná sọ láàárín àwùjọ wọn;Ọwọ́ iná jó àwọn ẹni burúkú run.+ 19  Wọ́n ṣe ère ọmọ màlúù kan ní Hórébù,Wọ́n sì forí balẹ̀ fún ère onírin;*+ 20  Wọ́n gbé ògo miFún ère akọ màlúù tó ń jẹ koríko.+ 21  Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run,+ Olùgbàlà wọn,Ẹni tó ṣe àwọn ohun ńlá ní Íjíbítì,+ 22  Àwọn iṣẹ́ àgbàyanu ní ilẹ̀ Hámù,+Àwọn ohun tó ń bani lẹ́rù ní Òkun Pupa.+ 23  Díẹ̀ ló kù kó sọ pé kí wọ́n pa wọ́n rẹ́,Àmọ́ Mósè àyànfẹ́ rẹ̀ bá wọn bẹ̀bẹ̀*Láti yí ìbínú rẹ̀ tó ń pani run pa dà.+ 24  Síbẹ̀, wọn ò ka ilẹ̀ dáradára náà sí;+Wọn ò nígbàgbọ́ nínú ìlérí rẹ̀.+ 25  Ṣe ni wọ́n ń ráhùn nínú àgọ́ wọn;+Wọn ò fetí sí ohùn Jèhófà.+ 26  Torí náà, ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè láti búra nípa wọnPé òun máa mú kí wọ́n ṣubú ní aginjù;+ 27  Pé òun máa mú kí àtọmọdọ́mọ wọn ṣubú láàárín àwọn orílẹ̀-èdèÀti pé òun máa tú wọn ká sí àwọn ilẹ̀ náà.+ 28  Lẹ́yìn náà, wọ́n dara pọ̀ mọ́ àwọn tó ń sin* Báálì Péórì,+Wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí wọ́n rú sí òkú.* 29  Wọ́n fi àwọn ohun tí wọ́n ń ṣe mú Un bínú,+Àjàkálẹ̀ àrùn sì bẹ́ sílẹ̀ láàárín wọn.+ 30  Àmọ́ nígbà tí Fíníhásì dìde, tí ó sì dá sí i,Àjàkálẹ̀ àrùn náà dáwọ́ dúró.+ 31  A sì kà á sí òdodo fún unLáti ìran dé ìran àti títí láé.+ 32  Wọ́n múnú bí I níbi omi Mẹ́ríbà,*Wọ́n sì fi tiwọn kó bá Mósè.+ 33  Wọ́n gbé ẹ̀mí rẹ̀ gbóná,Ó sì fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ láìronú.+ 34  Wọn ò pa àwọn èèyàn náà run,+Bí Jèhófà ṣe pàṣẹ fún wọn.+ 35  Àmọ́ wọ́n ń bá àwọn orílẹ̀-èdè náà ṣe wọlé wọ̀de,+Wọ́n sì ń hùwà bíi tiwọn.*+ 36  Wọ́n ń sin àwọn òrìṣà wọn,+Àwọn òrìṣà náà sì di ìdẹkùn fún wọn.+ 37  Wọ́n ń fi àwọn ọmọkùnrin wọnÀti àwọn ọmọbìnrin wọn rúbọ sí àwọn ẹ̀mí èṣù.+ 38  Wọ́n ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,+Ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin wọn àti ti àwọn ọmọbìnrin wọnTí wọ́n fi rúbọ sí àwọn òrìṣà Kénáánì;+Ilẹ̀ náà sì di ẹlẹ́gbin nítorí ìtàjẹ̀sílẹ̀. 39  Àwọn iṣẹ́ wọn sọ wọ́n di aláìmọ́,Wọ́n sì ṣe àgbèrè ẹ̀sìn.+ 40  Torí náà, ìbínú Jèhófà ru sí àwọn èèyàn rẹ̀,Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í kórìíra ogún rẹ̀. 41  Léraléra ló fi wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́,+Kí àwọn tó kórìíra wọn lè ṣàkóso lé wọn lórí.+ 42  Àwọn ọ̀tá wọn ni wọ́n lára,Wọ́n sì jẹ gàba lé wọn lórí.* 43  Ọ̀pọ̀ ìgbà ló gbà wọ́n sílẹ̀,+Àmọ́ wọ́n á ṣọ̀tẹ̀, wọ́n á sì ṣàìgbọràn,+A ó sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀ nítorí àṣìṣe wọn.+ 44  Àmọ́ á tún rí ìdààmú tó bá wọn,+Á sì gbọ́ igbe ìrànlọ́wọ́ wọn.+ 45  Nítorí wọn, á rántí májẹ̀mú rẹ̀,Àánú á sì ṣe é* nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tó ga tí kì í sì í yẹ̀.*+ 46  Á jẹ́ kí àánú wọn máa ṣeGbogbo àwọn tó mú wọn lẹ́rú.+ 47  Gbà wá, Jèhófà Ọlọ́run wa,+Kí o sì kó wa jọ látinú àwọn orílẹ̀-èdè+Ká lè máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ,Ká sì máa yọ̀ bí a ṣe ń yìn ọ́.*+ 48  Ìyìn ni fún Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lìTítí láé àti láéláé.*+ Kí gbogbo èèyàn sì sọ pé, “Àmín!”* Ẹ yin Jáà!*

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “Halelúyà!” “Jáà” ni ìkékúrú Jèhófà.
Tàbí “ṣoore fún.”
Tàbí “máa fi ọ́ yangàn.”
Tàbí “lóye ìtúmọ̀.”
Tàbí “aginjù.”
Tàbí “tó ṣẹ́ kù.”
Tàbí “ọkàn wọn.”
Tàbí “ère dídà.”
Ní Héb., “dúró sí àlàfo níwájú rẹ̀.”
Tàbí “so ara wọn mọ́.”
Ìyẹn, ẹbọ tí wọ́n rú sí òkú èèyàn tàbí sí àwọn ọlọ́run tí kò lẹ́mìí.
Ó túmọ̀ sí “Ìjà.”
Tàbí “Wọ́n sì kọ́ ìṣe wọn.”
Ní Héb., “Wọ́n sì wà lábẹ́ ọwọ́ wọn.”
Tàbí “Á kẹ́dùn.”
Tàbí “ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ tó pọ̀ gidigidi.”
Tàbí “yọ̀ nínú ìyìn rẹ.”
Tàbí “Láti ayérayé dé ayérayé.”
Tàbí “Kó rí bẹ́ẹ̀!”
Tàbí “Halelúyà!” “Jáà” ni ìkékúrú Jèhófà.