Jeremáyà 7:1-34
7 Ọ̀rọ̀ tí Jèhófà bá Jeremáyà sọ nìyí, ó ní:
2 “Dúró sí ẹnubodè ilé Jèhófà, kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀ pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Jèhófà, gbogbo ẹ̀yin èèyàn Júdà tó ń gba àwọn ẹnubodè yìí wọlé láti wá forí balẹ̀ fún Jèhófà.
3 Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí: “Ẹ tún ọ̀nà yín àti ìwà yín ṣe, màá sì jẹ́ kí ẹ máa gbé ibí yìí.+
4 Ẹ má ṣe gbẹ́kẹ̀ lé ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí wọ́n ń sọ pé, ‘Èyí ni* tẹ́ńpìlì Jèhófà, tẹ́ńpìlì Jèhófà, tẹ́ńpìlì Jèhófà!’+
5 Tí ẹ bá tún ọ̀nà yín àti ìwà yín ṣe lóòótọ́, tó bá sì jẹ́ pé òótọ́ lẹ ṣe ìdájọ́ òdodo láàárín èèyàn kan àti ọmọnìkejì rẹ̀,+
6 bí ẹ kò bá ni àjèjì lára àti ọmọ aláìlóbìí,* pẹ̀lú àwọn opó,+ tí ẹ kò ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, tí ẹ kò sì tẹ̀ lé àwọn ọlọ́run míì tó máa yọrí sí ìṣeléṣe yín; +
7 nígbà náà, màá jẹ́ kí ẹ máa gbé ibí yìí, ní ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.”’”*
8 “Àmọ́, ẹ̀ ń gbẹ́kẹ̀ lé ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn,+ kò ní ṣe yín láǹfààní kankan.
9 Ṣé ẹ lè máa jalè+ tàbí kí ẹ máa pa èèyàn, kí ẹ máa ṣe àgbèrè tàbí kí ẹ máa búra èké,+ kí ẹ máa rú ẹbọ* sí Báálì,+ kí ẹ sì máa tẹ̀ lé àwọn ọlọ́run míì tí ẹ kò mọ̀,
10 kí ẹ wá dúró níwájú mi nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, kí ẹ sì sọ pé, ‘A ó rí ìgbàlà,’ pẹ̀lú gbogbo ohun ìríra tí ẹ ti ṣe yìí?
11 Ṣé ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè ti wá di ihò tí àwọn olè ń fara pa mọ́ sí lójú yín ni?+ Èmi fúnra mi ti rí ohun tí ẹ̀ ń ṣe,” ni Jèhófà wí.
12 “‘Àmọ́, ní báyìí ẹ lọ sí àyè mi ní Ṣílò,+ níbi tí mo mú kí orúkọ mi wà ní ìbẹ̀rẹ̀,+ kí ẹ sì wo ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú àwọn èèyàn mi, Ísírẹ́lì.+
13 Ṣùgbọ́n ẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan yìí,’ ni Jèhófà wí, ‘àní bí mo tiẹ̀ bá yín sọ̀rọ̀ léraléra,* ẹ kò fetí sílẹ̀.+ Mo sì ń pè yín ṣáá, ṣùgbọ́n ẹ kò dá mi lóhùn.+
14 Bí mo ti ṣe sí Ṣílò, bẹ́ẹ̀ ni màá ṣe sí ilé tí a fi orúkọ mi pè,+ èyí tí ẹ gbẹ́kẹ̀ lé+ àti sí ibi tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba ńlá yín.+
15 Màá lé yín síta kúrò níwájú mi, bí mo ṣe lé gbogbo àwọn arákùnrin yín síta, gbogbo àwọn ọmọ Éfúrémù.’+
16 “Ní tìrẹ, má ṣe gbàdúrà nítorí àwọn èèyàn yìí. Má ṣe sunkún tàbí kí o gbàdúrà tàbí kí o bẹ̀ mí nítorí wọn,+ torí mi ò ní fetí sí ọ.+
17 Ṣé o ò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Júdà àti ní àwọn ojú ọ̀nà Jerúsálẹ́mù ni?
18 Àwọn ọmọ ń kó igi jọ, àwọn bàbá ń dá iná, àwọn ìyàwó sì ń po ìyẹ̀fun láti fi ṣe àkàrà ìrúbọ sí Ọbabìnrin Ọ̀run,*+ wọ́n sì ń da ọrẹ ohun mímu sí àwọn ọlọ́run míì láti mú mi bínú.+
19 ‘Àmọ́ ṣé èmi ni wọ́n ń mú bínú?’* ni Jèhófà wí. ‘Ǹjẹ́ kì í ṣe ara wọn ni wọn ń ṣe, tí wọ́n ń dójú ti ara wọn?’+
20 Torí náà, ohun tí Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ sọ nìyí, ‘Wò ó! Ìbínú mi àti ìrunú mi yóò dà sórí ibí yìí,+ sórí èèyàn àti ẹranko, sórí igi oko àti èso ilẹ̀. Ìbínú mi yóò máa jó bí iná tí kò ṣeé pa.’+
21 “Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí, ‘Ẹ lọ, kí ẹ fi odindi ẹbọ sísun yín kún àwọn ẹbọ yín yòókù, kí ẹ sì jẹ ẹran rẹ̀.+
22 Torí láti ọjọ́ tí mo ti mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì, mi ò bá wọn sọ̀rọ̀ tàbí kí n pàṣẹ fún wọn lórí àwọn odindi ẹbọ sísun àti àwọn ẹbọ.+
23 Ṣùgbọ́n, mo pàṣẹ fún wọn pé: “Ẹ gbọ́ràn sí mi lẹ́nu, màá sì di Ọlọ́run yín, ẹ ó sì di èèyàn mi.+ Kí ẹ máa rìn ní ọ̀nà tí mo pa láṣẹ fún yín, kí nǹkan lè máa lọ dáadáa fún yín.”’+
24 Ṣùgbọ́n wọn kò tẹ́tí sí mi, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sílẹ̀,+ kàkà bẹ́ẹ̀, wọ́n ń rìn nínú ètekéte* wọn, wọ́n ya alágídí, wọ́n sì ń ṣe ohun tí ọkàn búburú wọn sọ,+ ńṣe ni wọ́n ń pa dà sẹ́yìn, wọn ò lọ síwájú,
25 láti ọjọ́ tí àwọn baba ńlá yín ti jáde kúrò nílẹ̀ Íjíbítì títí di òní.+ Torí náà, mò ń rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì sí yín, mò ń rán wọn lójoojúmọ́, mo sì ń rán wọn léraléra.*+
26 Ṣùgbọ́n wọn kò tẹ́tí sí mi, wọn kò sì fetí sílẹ̀.+ Kàkà bẹ́ẹ̀, wọ́n ya alágídí,* wọ́n sì ṣe ohun tó burú ju ti àwọn baba ńlá wọn lọ!
27 “Wàá sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún wọn,+ ṣùgbọ́n wọn ò ní fetí sí ọ. Wàá pè wọ́n, ṣùgbọ́n wọn ò ní dá ọ lóhùn.
28 Wàá sì sọ fún wọn pé, ‘Orílẹ̀-èdè tí kò ṣègbọràn sí ohùn Jèhófà Ọlọ́run rẹ̀ nìyí, kò sì gba ìbáwí. Kò sí òtítọ́ mọ́, a ò tiẹ̀ gbúròó rẹ̀ láàárín wọn mọ́.’*+
29 “Fá irun gígùn* rẹ, kí o dà á nù, kí o sì kọ orin arò* lórí àwọn òkè, nítorí pé Jèhófà ti kọ ìran àwọn èèyàn tó mú un bínú yìí, yóò sì pa á tì.
30 ‘Nítorí àwọn èèyàn Júdà ti ṣe ohun tó burú ní ojú mi,’ ni Jèhófà wí. ‘Wọ́n ti gbé àwọn òrìṣà ẹ̀gbin wọn kalẹ̀ sínú ilé tí a fi orúkọ mi pè, láti sọ ọ́ di ẹlẹ́gbin.+
31 Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga Tófétì, èyí tó wà ní Àfonífojì Ọmọ Hínómù,*+ láti sun àwọn ọmọkùnrin wọn àti àwọn ọmọbìnrin wọn nínú iná,+ ohun tí mi ò pa láṣẹ, tí kò sì wá sí mi lọ́kàn rí.’*+
32 “‘Nítorí náà, wò ó! ọjọ́ ń bọ̀,’ ni Jèhófà wí, ‘tí a kò ní pè é ní Tófétì tàbí Àfonífojì Ọmọ Hínómù mọ́,* àmọ́ Àfonífojì Ìpànìyàn la ó máa pè é. Wọ́n á sin òkú ní Tófétì títí kò fi ní sí àyè mọ́.+
33 Òkú àwọn èèyàn yìí á di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀, láìsí ẹnikẹ́ni tó máa lé wọn dà nù.+
34 Màá fòpin sí ìró ayọ̀ àti ìró ìdùnnú, ohùn ọkọ ìyàwó àti ohùn ìyàwó+ ní àwọn ìlú Júdà àti ní àwọn ojú ọ̀nà Jerúsálẹ́mù, nítorí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.’”+
Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
^ Ní Héb., “Wọ́n jẹ́,” ìyẹn gbogbo àwọn ilé tó wà ní tẹ́ńpìlì náà.
^ Tàbí “àwọn ọmọ aláìníbaba.”
^ Tàbí “láti ayérayé dé ayérayé.”
^ Tàbí “mú ẹbọ rú èéfín.”
^ Ní Héb., “dìde ní kùtùkùtù láti bá yín sọ̀rọ̀.”
^ Orúkọ oyè abo ọlọ́run tí àwọn èèyàn Ísírẹ́lì apẹ̀yìndà ń jọ́sìn; ó ṣeé ṣe kó jẹ́ abo ọlọ́run ìbímọlémọ.
^ Tàbí “ṣẹ̀ sí?”
^ Tàbí “ìmọ̀ràn.”
^ Ní Héb., “mò ń jí ní kùtùkùtù lójoojúmọ́, mo sì ń rán wọn.”
^ Ní Héb., “wọ́n mú ọrùn wọn le.”
^ Ní Héb., “a ti gé e kúrò ní ẹnu wọn.”
^ Tàbí “irun ìyàsọ́tọ̀.”
^ Tàbí “orin ọ̀fọ̀.”
^ Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀, “Gẹ̀hẹ́nà.”
^ Tàbí “ohun tí èmi kò ronú rẹ̀ rí.”
^ Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀, “Gẹ̀hẹ́nà.”

