Jóòbù 6:1-30
6 Jóòbù wá fèsì pé:
2 “Ká ní wọ́n lè díwọ̀n ìrora mi+ látòkè délẹ̀ ni,Kí wọ́n sì gbé òun àti àjálù mi sórí òṣùwọ̀n!
3 Ó ti wá wúwo ju iyanrìn òkun lọ báyìí.
Ìdí nìyẹn tí ọ̀rọ̀ mi fi jẹ́ ọ̀rọ̀ ẹhànnà.*+
4 Torí àwọn ọfà Olódùmarè ti gún mi,Ẹ̀mí mi sì ń mu oró wọn;+Ohun tó ń fa ìpayà látọ̀dọ̀ Ọlọ́run ti kóra jọ lòdì sí mi.
5 Ṣé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó+ máa ké tó bá rí koríko jẹ,Àbí ṣé akọ màlúù máa dún tó bá rí oúnjẹ ẹran jẹ?
6 Ṣé èèyàn lè jẹ oúnjẹ tí kò dùn láìfi iyọ̀ sí i,Àbí ṣé adùn wà nínú omi ewéko málò?
7 Mi* ò fọwọ́ kan irú àwọn nǹkan yẹn.
Wọ́n dà bí ohun tó ba oúnjẹ mi jẹ́.
8 Ká ní ọwọ́ mi lè tẹ ohun tí mo béèrè ni,Kí Ọlọ́run sì ṣe ohun tí mo fẹ́ fún mi!
9 Pé kí Ọlọ́run ṣe tán láti tẹ̀ mí rẹ́,Kó na ọwọ́ rẹ̀, kó sì pa mí dà nù!+
10 Torí ìyẹn gan-an máa tù mí nínú;Màá fò sókè tayọ̀tayọ̀ láìka ìrora tí kò lọ sí,Torí mi ò sọ pé irọ́ ni àwọn ọ̀rọ̀ Ẹni Mímọ́.+
11 Ṣé agbára mi gbé e láti máa dúró?+
Òpin wo ló máa dé bá mi, tí màá ṣì fi wà láàyè?*
12 Ṣé mo lágbára bí òkúta?
Àbí bàbà ni ẹran ara mi?
13 Ṣé mo lè ran ara mi lọ́wọ́ rárá,Nígbà tí a ti lé gbogbo ohun tí mo fi ń ti ara mi lẹ́yìn jìnnà sí mi?
14 Ẹnikẹ́ni tí kò bá fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn sí ẹnì kejì rẹ̀,+Kò ní bẹ̀rù Olódùmarè.+
15 Àwọn arákùnrin mi ti di ọ̀dàlẹ̀+ bí odò ìgbà òtútù,Bí àwọn omi odò ìgbà òtútù tó gbẹ.
16 Yìnyín mú kó ṣókùnkùn,Yìnyín tó sì ń yọ́ fara pa mọ́ sínú wọn.
17 Àmọ́ ní àsìkò tó yẹ, wọn ò lómi mọ́, wọ́n sì wá sí òpin;Nígbà ẹ̀ẹ̀rùn, wọ́n gbẹ dà nù.
18 Ipa odò wọn gba ibòmíì;Wọ́n ṣàn lọ sínú aṣálẹ̀, wọ́n sì dópin.
19 Àwọn ará Témà+ tí wọ́n ń rìnrìn àjò ń wá wọn,Àwọn arìnrìn-àjò láti Ṣébà*+ ń dúró dè wọ́n.
20 Ojú tì wọ́n torí pé ìgbẹ́kẹ̀lé wọn ti dòfo;Wọ́n dé ibẹ̀, àmọ́ òfo ni wọ́n bá.
21 Bí ẹ̀yin náà ṣe wá rí lójú mi nìyẹn;+Ẹ rí bí àjálù tó bá mi ṣe le tó,* ẹ̀rù sì bà yín.+
22 Ṣé mo sọ pé, ‘Ẹ fún mi ní nǹkan,’Àbí mo tọrọ ẹ̀bùn látinú ọrọ̀ yín?
23 Ṣé mo ní kí ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá,Àbí mo ní kí ẹ gbà mí* lọ́wọ́ àwọn tó ń fìyà jẹ mí?
24 Ẹ kọ́ mi, màá sì dákẹ́;+Ẹ jẹ́ kí n mọ àṣìṣe mi.
25 Òótọ́ ọ̀rọ̀ kì í dunni!+
Àmọ́ kí ni ìbáwí yín wúlò fún?+
26 Ṣé ẹ̀ ń gbèrò láti bá mi wí torí ọ̀rọ̀ mi ni,Ọ̀rọ̀ tí ẹni tí ìdààmú bá ń sọ,+ tí afẹ́fẹ́ sì ń fẹ́ dà nù?
27 Ẹ máa ṣẹ́ kèké lé ọmọ aláìlóbìí*+ pàápàá,Ẹ sì máa ta ọ̀rẹ́ yín!*+
28 Torí náà, ẹ yíjú wò mí,Mi ò ní parọ́ fún yín.
29 Ẹ jọ̀ọ́, ẹ tún inú rò, ẹ má ṣe dá mi lẹ́bi,Àní, ẹ tún inú rò, torí òdodo mi ò tíì yí pa dà.
30 Ṣé ahọ́n mi ń sọ ohun tí kò tọ́ ni?
Ṣé agbára ìtọ́wò ẹnu mi ò mọ̀ pé nǹkan ti ṣẹlẹ̀ ni?

