Jóòbù 40:1-24

  • Jèhófà tún bi í láwọn ìbéèrè (1-24)

    • Jóòbù gbà pé òun ò ní nǹkan kan láti sọ (3-5)

    • “Ṣé o máa sọ pé mi ò ṣèdájọ́ bó ṣe tọ́ ni?” (8)

    • Ọlọ́run jẹ́ ká mọ bí Béhémótì ṣe lágbára tó (15-24)

40  Jèhófà ń fún Jóòbù lésì nìṣó pé:   “Ṣó yẹ kí ẹni tó ń wá ẹ̀sùn bá Olódùmarè fa ọ̀rọ̀?+ Kí ẹni tó fẹ́ bá Ọlọ́run wí fèsì.”+   Jóòbù dá Jèhófà lóhùn pé:   “Wò ó! Mi ò já mọ́ nǹkan kan.+ Kí ni màá fi dá ọ lóhùn? Mo fi ọwọ́ bo ẹnu mi.+   Mo ti sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kan, àmọ́ mi ò ní dáhùn mọ́;Lẹ́ẹ̀kejì, mi ò sì ní sọ̀rọ̀ mọ́.”  Ni Jèhófà bá dá Jóòbù lóhùn látinú ìjì, ó ní:+   “Jọ̀ọ́, gbára dì, kí o ṣe bí ọkùnrin;Màá bi ọ́ ní ìbéèrè, kí o sì dá mi lóhùn.+   Ṣé o máa sọ pé mi ò ṣèdájọ́ bó ṣe tọ́ ni?* Ṣé o máa dá mi lẹ́bi kí o lè jàre?+   Ṣé o ní apá tó lágbára bíi ti Ọlọ́run tòótọ́,+ Àbí ṣé ohùn rẹ lè sán ààrá bíi tirẹ̀?+ 10  Jọ̀ọ́, fi ògo àti ọlá ńlá ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́;Kí o sì fi iyì àti ẹwà wọ ara rẹ láṣọ. 11  Tú ìbínú rẹ tó ń ru jáde;Wo gbogbo ẹni tó ń gbéra ga, kí o sì rẹ̀ wọ́n nípò wálẹ̀. 12  Wo gbogbo ẹni tó ń gbéra ga, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀,Kí o sì tẹ àwọn ẹni burúkú mọ́lẹ̀ níbi tí wọ́n dúró sí. 13  Fi wọ́n pa mọ́ sínú erùpẹ̀;Dè wọ́n* síbi tó fara sin, 14  Nígbà náà, èmi pàápàá á sọ fún ọ* pé,Ọwọ́ ọ̀tún rẹ lè gbà ọ́ là. 15  Wò ó, Béhémótì* nìyí, tí mo dá bí mo ṣe dá ọ. Ó ń jẹ koríko bí akọ màlúù. 16  Wo bí ìbàdí rẹ̀ ṣe lágbáraÀti bí àwọn iṣan ikùn rẹ̀ ṣe lágbára tó! 17  Ó ń mú kí ìrù rẹ̀ le bí igi kédárì;A hun àwọn iṣan itan rẹ̀ pọ̀. 18  Àwọn egungun rẹ̀ dà bí ọ̀pá bàbà oníhò;Apá àti ẹsẹ̀ rẹ̀ dà bí ọ̀pá irin tó lágbára. 19  Ó wà ní ipò kìíní* lára àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run;Aṣẹ̀dá rẹ̀ nìkan ló lè mú idà rẹ̀ sún mọ́ ọn. 20  Torí àwọn òkè ló ń pèsè oúnjẹ fún un,Níbi tí gbogbo àwọn ẹran igbó ti ń ṣeré. 21  Ó dùbúlẹ̀ sábẹ́ àwọn igi lótọ́sì,Lábẹ́ òjìji àwọn esùsú* níbi irà. 22  Àwọn igi lótọ́sì ṣíji bò ó,Àwọn igi pọ́pílà tó wà ní àfonífojì sì yí i ká. 23  Tí odò bá ń ru gùdù, kì í bẹ̀rù. Ọkàn rẹ̀ balẹ̀, bí Jọ́dánì+ tiẹ̀ ń ya lu ẹnu rẹ̀. 24  Ṣé ẹnikẹ́ni lè mú un tó bá ń wò,Àbí kó fi ìwọ̀* kọ́ ọ ní imú?

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ìdájọ́ mi kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ ni.”
Ní Héb., “De ojú wọn.”
Tàbí “yìn ọ́.”
Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ erinmi.
Ní Héb., “Òun ni ìbẹ̀rẹ̀.”
Iyẹn, koríko etí omi.
Ní Héb., “ìdẹkùn.”