Jóòbù 3:1-26

  • Jóòbù ń kábàámọ̀ ọjọ́ tí wọ́n bí i (1-26)

    • Ó béèrè ohun tó fa ìyà òun (20, 21)

3  Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jóòbù bẹ̀rẹ̀ sí í sọ̀rọ̀, ó sì ń fi ọjọ́ tí wọ́n bí i gégùn-ún.*+  Jóòbù sọ pé:   “Kí ọjọ́ tí wọ́n bí mi + ṣègbé,Àti òru tí ẹnì kan sọ pé: ‘Wọ́n ti lóyún ọkùnrin kan!’   Kí ọjọ́ yẹn ṣókùnkùn. Kí Ọlọ́run lókè má ka ọjọ́ yẹn sí;Kí ìmọ́lẹ̀ má tàn sórí rẹ̀ rárá.   Kí òkùnkùn biribiri* gbà á pa dà. Kí òjò ṣú bò ó. Kí ohunkóhun tó ń mú ojúmọ́ ṣókùnkùn dẹ́rù bà á.   Kí ìṣúdùdù gba òru yẹn;+Kó má ṣe yọ̀ láàárín àwọn ọjọ́ tó wà nínú ọdún,Kí wọ́n má sì kà á mọ́ àwọn oṣù.   Àní, kí òru yẹn yàgàn! Ká má ṣe gbọ́ igbe ayọ̀ kankan ní òru yẹn.   Kí àwọn tó ń fi ọjọ́ gégùn-ún fi í gégùn-ún,Àwọn tó lè mú kí Léfíátánì*+ sọ jí.   Kí àwọn ìràwọ̀ rẹ̀ ṣókùnkùn ní ìdájí;Kó dúró de ìmọ́lẹ̀, àmọ́ kí ìrètí rẹ̀ já sí asán,Kó má sì rí ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀. 10  Torí kò ti àwọn ilẹ̀kùn ilé ọlẹ̀ ìyá mi;+Kò sì pa ojú mi mọ́ kúrò nínú wàhálà. 11  Kí ló dé tí mi ò kú nígbà tí wọ́n bí mi? Kí ló dé tí mi ò ṣègbé nígbà tí mo jáde látinú ikùn?+ 12  Kí ló dé tí orúnkún tó gbà mí fi wà,Tí ọmú tí màá mu sì wà? 13  Torí mi ò bá máa dùbúlẹ̀ báyìí láìsí ìyọlẹ́nu;+Mi ò bá máa sùn, kí n sì máa sinmi+ 14  Pẹ̀lú àwọn ọba ayé àti àwọn agbani-nímọ̀ràn wọn,Tí wọ́n kọ́ àwọn ibi tó ti di àwókù báyìí fún ara wọn,* 15  Tàbí pẹ̀lú àwọn ìjòyè tó ní wúrà,Àwọn tí fàdákà kún ilé wọn. 16  Àbí kí ló dé tí oyún mi ò ti bà jẹ́ kí wọ́n tó mọ̀,Bí àwọn ọmọ tí kò rí ìmọ́lẹ̀ rárá? 17  Ibẹ̀ ni àwọn ẹni burúkú pàápàá ti bọ́ lọ́wọ́ ìdààmú;Ibẹ̀ ni àwọn tí kò lókun ti ń sinmi.+ 18  Ibẹ̀ ni ara ti tu àwọn ẹlẹ́wọ̀n pa pọ̀;Wọn ò gbọ́ ohùn ẹni tó ń fipá kó wọn ṣiṣẹ́. 19  Ẹni kékeré àti ẹni ńlá ò jura wọn lọ níbẹ̀,+Ẹrú sì dòmìnira lọ́wọ́ ọ̀gá rẹ̀. 20  Kí ló dé tó fún ẹni tí ìyà ń jẹ ní ìmọ́lẹ̀,Tó sì fún àwọn tó ní ẹ̀dùn ọkàn*+ ní ìyè? 21  Kí ló dé tí wọ́n ń retí ikú, àmọ́ tí kò dé?+ Wọ́n ń wá a ju bí wọ́n ṣe ń wá ìṣúra tó fara pa mọ́ sínú ilẹ̀, 22  Àwọn tí inú wọn ń dùn gidigidi,Tí wọ́n ń yọ̀ nígbà tí wọ́n rí sàréè. 23  Kí ló dé tó fún ẹni tó ṣìnà ní ìmọ́lẹ̀,Ẹni tí Ọlọ́run ti sé mọ́?+ 24  Ẹ̀dùn ọkàn ti dípò oúnjẹ mi,+Ìkérora mi+ sì ń tú jáde bí omi. 25  Torí ohun tí mo bẹ̀rù ti dé bá mi,Ohun tó sì ń já mi láyà ti ṣẹlẹ̀ sí mi. 26  Mi ò ní àlàáfíà, ọkàn mi ò balẹ̀, mi ò sì sinmi,Síbẹ̀, wàhálà ò yéé dé bá mi.”

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Héb., “gégùn-ún fún ọjọ́ rẹ̀.”
Tàbí “òkùnkùn àti òjìji ikú.”
Ohun tí a mọ̀ ọ́n sí ni ọ̀nì tàbí ẹran míì tó tóbi, tó lágbára, tó sì ń gbé inú omi.
Tàbí kó jẹ́, “kọ́ àwọn ibi tó ti di ahoro fún ara wọn.”
Tàbí “tí ọkàn wọn gbọgbẹ́.”