Jóòbù 29:1-25
29 Jóòbù ń bá ọ̀rọ̀* rẹ̀ lọ, ó ní:
2 “Ká sọ pé àwọn oṣù tó ti kọjá ni mo wà,Láwọn ọjọ́ tí Ọlọ́run ń ṣọ́ mi,
3 Nígbà tó mú kí fìtílà rẹ̀ tàn sí mi lórí,Nígbà tí mo fi ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ rìn nínú òkùnkùn,+
4 Nígbà tí mo ṣì lókun,*Nígbà tí mo mọ bó ṣe ń rí kéèyàn jẹ́ ọ̀rẹ́ Ọlọ́run nínú àgọ́ mi,+
5 Nígbà tí Olódùmarè ṣì wà pẹ̀lú mi,Nígbà tí àwọn ọmọ* mi yí mi ká,
6 Nígbà tí bọ́tà bo àwọn ìṣísẹ̀ mi,Tí àwọn àpáta sì ń tú ìṣàn òróró jáde fún mi.+
7 Nígbà tí mo ṣì máa ń jáde lọ sí ẹnubodè ìlú,+Tí mo sì máa ń jókòó sí ojúde ìlú,+
8 Àwọn ọ̀dọ́kùnrin máa rí mi, wọ́n á sì yà sẹ́gbẹ̀ẹ́,*Àwọn àgbà ọkùnrin pàápàá máa dìde, wọ́n á sì wà ní ìdúró.+
9 Àwọn ìjòyè máa ń dákẹ́;Wọ́n á fi ọwọ́ bo ẹnu wọn.
10 Àwọn gbajúmọ̀ ọkùnrin panu mọ́;Ahọ́n wọn lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn.
11 Ẹnikẹ́ni tó bá gbọ́ mi máa ń sọ̀rọ̀ mi dáadáa,Àwọn tó sì rí mi máa ń ṣe ẹlẹ́rìí mi.
12 Torí mo máa ń gba aláìní tó ń kígbe fún ìrànlọ́wọ́ sílẹ̀,+Pẹ̀lú ọmọ aláìníbaba* àti ẹnikẹ́ni tí kò ní olùrànlọ́wọ́.+
13 Ẹni tó ń kú lọ máa ń súre fún mi,+Mo sì ń mú kí inú opó dùn.+
14 Mo wọ òdodo bí aṣọ;Ìdájọ́ òdodo mi dà bí ẹ̀wù* àti láwàní.
15 Mo di ojú fún afọ́júÀti ẹsẹ̀ fún arọ.
16 Mo jẹ́ bàbá fún àwọn aláìní;+Mo máa ń wádìí ẹjọ́ àwọn tí mi ò mọ̀.+
17 Mo máa ń fọ́ páárì ẹ̀rẹ̀kẹ́ ẹni burúkú,+Mo sì máa ń já ẹran gbà kúrò ní eyín rẹ̀.
18 Mo máa ń sọ pé, ‘Inú ilé mi* ni màá kú sí,+Ọjọ́ ayé mi á sì pọ̀ bí iyanrìn.
19 Màá ta gbòǹgbò wọnú omi,Ìrì á sì wà lórí àwọn ẹ̀ka mi mọ́jú.
20 Ògo mi ń di ọ̀tun ní gbogbo ìgbà,Màá sì máa ta ọfà ọwọ́ mi léraléra.’
21 Àwọn èèyàn máa ń fẹ́ gbọ́ mi,Wọ́n á dákẹ́, wọ́n á máa retí ìmọ̀ràn mi.+
22 Tí mo bá ti sọ̀rọ̀, wọn kì í tún ní ohunkóhun láti sọ;Ọ̀rọ̀ mi máa ń rọra wọ̀ wọ́n* létí.
23 Wọ́n ń dúró dè mí bí ẹni ń dúró de òjò;Wọ́n la ẹnu wọn sílẹ̀ gbayawu bíi fún òjò ìrúwé.+
24 Nígbà tí mo rẹ́rìn-ín músẹ́ sí wọn, ó yà wọ́n lẹ́nu gan-an;Ìmọ́lẹ̀ ojú mi máa ń fi wọ́n lọ́kàn balẹ̀.*
25 Mò ń darí wọn gẹ́gẹ́ bí olórí wọn,Mo sì ń gbé bí ọba láàárín àwọn ọmọ ogun rẹ̀,+Bí ẹni tó ń tu àwọn tó ń ṣọ̀fọ̀ nínú.+

