Jóòbù 18:1-21

  • Ìgbà kejì tí Bílídádì sọ̀rọ̀ (1-21)

    • Ó sọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ (5-20)

    • Ó ń dọ́gbọ́n sọ pé Jóòbù kò mọ Ọlọ́run (21)

18  Bílídádì+ ọmọ Ṣúáhì fèsì pé:   “Ìgbà wo lẹ ò ní sọ̀rọ̀ báyìí mọ́? Ẹ lo òye, ká lè wá sọ̀rọ̀.   Kí ló dé tí ẹ̀ ń fojú ẹranko wò wá,+Tí ẹ sì kà wá sí òpònú?*   Tí o bá tiẹ̀ fa ara* rẹ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ torí inú tó ń bí ọ,Ṣé a máa pa ayé tì nítorí rẹ ni,Àbí àpáta máa ṣí kúrò ní àyè rẹ̀?   Àní, a máa pa iná ẹni burúkú,Ọwọ́ iná rẹ̀ kò sì ní tàn.+   Ó dájú pé ìmọ́lẹ̀ inú àgọ́ rẹ̀ máa di òkùnkùn,A sì máa fẹ́ fìtílà tó wà lórí rẹ̀ pa.   Ìrìn tó ń fi tagbáratagbára rìn dín kù,Ìmọ̀ràn ara rẹ̀ sì máa gbé e ṣubú.+   Torí ẹsẹ̀ rẹ̀ máa mú un wọnú àwọ̀n,Ó sì máa rìn gbéregbère wọnú àwọn okùn rẹ̀.   Pańpẹ́ máa mú un ní gìgísẹ̀;Ìdẹkùn á sì mú un.+ 10  Okùn kan ti wà nípamọ́ dè é lórí ilẹ̀,Pańpẹ́ sì wà lójú ọ̀nà rẹ̀. 11  Jìnnìjìnnì bò ó yí ká,+Ó sì ń sá tẹ̀ lé e ní ẹsẹ̀ rẹ̀. 12  Okun tán nínú rẹ̀,Àjálù+ sì máa mú kó ta gọ̀ọ́gọ̀ọ́.* 13  Awọ ara rẹ̀ jẹ dà nù;Àìsàn gbẹ̀mí-gbẹ̀mí tó lágbára jù* jẹ apá àti ẹsẹ̀ rẹ̀ run. 14  Wọ́n fà á kúrò nínú àgọ́ rẹ̀ tí ààbò wà,+Lọ sọ́dọ̀ ọba ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀.* 15  Àwọn àjèjì* á máa gbé inú àgọ́ rẹ̀;A máa fọ́n imí ọjọ́ sórí ilé rẹ̀.+ 16  Gbòǹgbò rẹ̀ máa gbẹ lábẹ́ rẹ̀,Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì máa rọ lórí rẹ̀. 17  Wọn ò ní rántí rẹ̀ mọ́ ní ayé,Wọn ò sì ní mọ orúkọ rẹ̀* ní àdúgbò. 18  Wọ́n máa lé e kúrò nínú ìmọ́lẹ̀ sínú òkùnkùn,Wọ́n sì máa lé e kúrò ní ilẹ̀ tó ń méso jáde. 19  Kò ní ní ọmọ àti àtọmọdọ́mọ láàárín àwọn èèyàn rẹ̀,Kò sì ní sí ẹni tó máa yè bọ́ níbi tó ń gbé.* 20  Tí ọjọ́ rẹ̀ bá dé, àwọn èèyàn tó wà ní Ìwọ̀ Oòrùn máa bẹ̀rù,Jìnnìjìnnì sì máa bo àwọn èèyàn tó wà ní Ìlà Oòrùn. 21  Ohun tó máa ń ṣẹlẹ̀ sí àgọ́ ẹni burúkú nìyíÀti ibùgbé ẹni tí kò mọ Ọlọ́run.”

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí kó jẹ́, “aláìmọ́.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “tiro.”
Ní Héb., “Àkọ́bí ikú.”
Tàbí “ikú oró.”
Ní Héb., “Ohun tí kì í ṣe tirẹ̀.”
Ní Héb., “Orúkọ rẹ̀ ò sì ní sí.”
Tàbí “níbi tó ń gbé fúngbà díẹ̀.”