Jóòbù 14:1-22

  • Jóòbù ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ (1-22)

    • Èèyàn jẹ́ ọlọ́jọ́ kúkúrú, wàhálà tó bá a pọ̀ gan-an (1)

    • “Ìrètí wà fún igi pàápàá” (7)

    • “Ká ní o lè fi mí pa mọ́ sínú Isà Òkú ni” (13)

    • “Tí èèyàn bá kú, ṣé ó tún lè wà láàyè?” (14)

    • Ó máa wu Ọlọ́run gan-an pé kó rí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ (15)

14  “Èèyàn tí obìnrin bí,Ọlọ́jọ́ kúkúrú ni,+ wàhálà* rẹ̀ sì máa ń pọ̀ gan-an.+   Ó jáde wá bí ìtànná, ó sì rọ dà nù;*+Ó ń sá lọ bí òjìji, ó sì pòórá.+   Àní, o ti tẹjú mọ́ ọn,O sì ti bá a* ṣe ẹjọ́.+   Ta ló lè mú ẹni tó mọ́ jáde látinú ẹni tí kò mọ́?+ Kò sẹ́ni tó lè ṣe é!   Tí a bá ti pinnu àwọn ọjọ́ rẹ̀,Iye oṣù rẹ̀ wà lọ́wọ́ rẹ;O ti pààlà fún un, kó má bàa kọjá rẹ̀.+   Gbé ojú rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ kó lè sinmi,Títí ó fi máa lo ọjọ́ rẹ̀ tán+ bí alágbàṣe.   Torí ìrètí wà fún igi pàápàá. Tí wọ́n bá gé e lulẹ̀, ó máa hù pa dà,Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ á sì máa dàgbà.   Tí gbòǹgbò rẹ̀ bá gbó sínú ilẹ̀,Tí kùkùté rẹ̀ sì kú sínú iyẹ̀pẹ̀,   Ó máa hù tó bá gbúròó omi;Ó sì máa yọ ẹ̀ka bí ewéko tó ṣẹ̀ṣẹ̀ hù. 10  Àmọ́ èèyàn kú, ó sì wà nílẹ̀ láìlágbára;Tí èèyàn bá gbẹ́mìí mì, ibo ló wà?+ 11  Omi dàwátì nínú òkun,Odò ń fà, ó sì gbẹ táútáú. 12  Bẹ́ẹ̀ ni èèyàn ń dùbúlẹ̀, kì í sì í dìde.+ Títí ọ̀run kò fi ní sí mọ́, wọn ò ní jí,Bẹ́ẹ̀ ni a ò ní jí wọn lójú oorun.+ 13  Ká ní o lè fi mí pa mọ́ sínú Isà Òkú* ni,+Kí o fi mí pa mọ́ títí ìbínú rẹ fi máa kọjá,Kí o yan àkókò kan sílẹ̀ fún mi, kí o sì rántí mi!+ 14  Tí èèyàn bá kú, ṣé ó tún lè wà láàyè?+ Màá dúró jálẹ̀ gbogbo ọjọ́ tó pọn dandan pé kí n lò,Títí ìtura mi fi máa dé. + 15  O máa pè, màá sì dá ọ lóhùn.+ Ó máa wù ọ́ gan-an láti rí* iṣẹ́ ọwọ́ rẹ. 16  Àmọ́ ní báyìí, ò ń ka gbogbo ìṣísẹ̀ mi ṣáá;Ẹ̀ṣẹ̀ mi nìkan lò ń ṣọ́. 17  O sé ẹ̀ṣẹ̀ mi mọ́ inú àpò,O sì fi àtè lẹ àṣìṣe mi pa. 18  Bí òkè ṣe máa ń ṣubú, tó sì ń fọ́ sí wẹ́wẹ́,Tí àpáta sì ń ṣí kúrò ní àyè rẹ̀, 19  Bí omi ṣe ń mú kí òkúta yìnrìn,Tí ọ̀gbàrá rẹ̀ sì ń wọ́ iyẹ̀pẹ̀ ilẹ̀. Bẹ́ẹ̀ lo ṣe sọ ìrètí ẹni kíkú dòfo. 20  Ò ń borí rẹ̀ títí ó fi ṣègbé;+O yí ìrísí rẹ̀ pa dà, o sì ní kó máa lọ. 21  A bọlá fún àwọn ọmọ rẹ̀, àmọ́ kò mọ̀;Wọ́n di ẹni tí kò ní láárí, àmọ́ kò mọ̀.+ 22  Ìgbà tó ṣì jẹ́ ẹlẹ́ran ara nìkan ló mọ̀ pé òun ń jẹ̀rora;Ìgbà tí ó* ṣì wà láàyè nìkan ló ń ṣọ̀fọ̀.”

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ṣìbáṣìbo.”
Tàbí kó jẹ́, “a sì ké e kúrò.”
Ní Héb., “mi.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “O máa yán hànhàn fún.”
Tàbí “ọkàn rẹ̀.”