Jóòbù 13:1-28

  • Jóòbù ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ (1-28)

    • ‘Màá kúkú bá Ọlọ́run sọ̀rọ̀’ (3)

    • ‘Oníṣègùn tí kò wúlò ni yín’ (4)

    • “Mo mọ̀ pé èmi ni mo jàre” (18)

    • Ó fẹ́ mọ ìdí tí Ọlọ́run fi ka òun sí ọ̀tá (24)

13  “Àní ojú mi ti rí gbogbo èyí,Etí mi ti gbọ́, ó sì ti yé mi.   Ohun tí ẹ mọ̀ ni èmi náà mọ̀;Mi ò kéré sí yín.   Ní tèmi, màá kúkú bá Olódùmarè fúnra rẹ̀ sọ̀rọ̀;Ọlọ́run ni mo fẹ́ ro ẹjọ́ mi fún.+   Ẹ̀ ń fi irọ́ bà mí lórúkọ jẹ́;Oníṣègùn tí kò wúlò ni gbogbo yín.+   Ká ní ẹ lè dákẹ́ láìsọ nǹkan kan ni,Ìyẹn ì bá fi hàn pé ẹ jẹ́ ọlọ́gbọ́n!+   Ẹ jọ̀ọ́, ẹ tẹ́tí gbọ́ àlàyé mi,Kí ẹ sì fiyè sí àrọwà ètè mi.   Ṣé ẹ máa sọ̀rọ̀ tí kò tọ́ láti gbèjà Ọlọ́run,Ṣé ẹ fẹ́ sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn láti gbè é lẹ́yìn?   Ṣé ẹ máa gbè sẹ́yìn rẹ̀,*Ṣé ẹ fẹ́ máa gbèjà Ọlọ́run tòótọ́ ni?   Tó bá yẹ̀ yín wò, ṣé ibi tó dáa ló máa já sí?+ Àbí ẹ máa tàn án jẹ bí ẹ ṣe máa tan ẹni kíkú? 10  Tí ẹ bá gbìyànjú láti ṣe ojúsàájú níkọ̀kọ̀,+Ó dájú pé ó máa bá yín wí. 11  Ṣé iyì rẹ̀ pàápàá kò ní kó jìnnìjìnnì bá yín,Ṣé ẹ̀rù rẹ̀ kò sì ní bà yín? 12  Àwọn ọ̀rọ̀ ọgbọ́n* yín jẹ́ òwe tó dà bí eérú;Àwọn ohun tí ẹ fi ń gbèjà ara yín* ò lágbára, wọ́n dà bí ohun tí wọ́n fi amọ̀ ṣe. 13  Ẹ dákẹ́ níwájú mi, kí n lè sọ̀rọ̀. Kí ohunkóhun tó bá wá fẹ́ ṣẹlẹ̀ sí mi ṣẹlẹ̀! 14  Kí ló dé tí mo fi ara mi sínú ewu,*Tí mo sì fi ẹ̀mí* mi sọ́wọ́ mi? 15  Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ó lè pa mí, màá ṣì dúró;+Màá ro ẹjọ́ mi* níwájú rẹ̀. 16  Ó máa wá di ìgbàlà mi,+Torí ẹni tí kò mọ Ọlọ́run* kò lè wá síwájú rẹ̀.+ 17  Ẹ fetí sílẹ̀ dáadáa sí ọ̀rọ̀ mi;Ẹ fiyè sí ohun tí mo fẹ́ sọ. 18  Ẹ wò ó, mo ti múra ẹjọ́ mi sílẹ̀ báyìí;Mo mọ̀ pé èmi ni mo jàre. 19  Ta ló máa bá mi fà á? Màá kú tí mo bá dákẹ́!* 20  Ohun méjì péré ni kí o ṣe fún mi, ìwọ Ọlọ́run,*Kí n má bàa fi ara mi pa mọ́ níwájú rẹ: 21  Gbé ọwọ́ rẹ tó wúwo jìnnà réré sí mi,Má sì jẹ́ kí ẹ̀rù rẹ kó jìnnìjìnnì bá mi.+ 22  Nínú kí o pè, kí n sì dá ọ lóhùn,Tàbí kí o jẹ́ kí n sọ̀rọ̀, kí o sì dá mi lóhùn. 23  Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀, kí sì ni àṣìṣe mi? Jẹ́ kí n mọ ìṣìnà mi àti ẹ̀ṣẹ̀ mi. 24  Kí ló dé tí o fi ojú rẹ pa mọ́,+Tí o sì kà mí sí ọ̀tá rẹ?+ 25  Ṣé o máa fẹ́ dẹ́rù ba ewé tí afẹ́fẹ́ ń gbé kiri ni,Àbí o fẹ́ máa sáré lé àgékù pòròpórò tó ti gbẹ? 26  Torí ò ń fẹ̀sùn tó le kàn mí, o sì ń kọ ọ́ sílẹ̀ ṣáá,O sì mú kí n jìyà àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí mo dá nígbà tí mo ṣì kéré. 27  O ti ẹsẹ̀ mi mọ́ inú àbà,Ò ń ṣọ́ gbogbo ọ̀nà mi lójú méjèèjì,O sì ń wá ipasẹ̀ mi jáde lọ́kọ̀ọ̀kan. 28  Torí náà, èèyàn* ń jẹrà bí ohun tó ti rà,Bí aṣọ tí òólá* ti jẹ.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ṣe ojúsàájú sí i.”
Tàbí “ọ̀rọ̀ ìrántí.”
Ní Héb., “kókó rubutu orí apata yín.”
Ní Héb., “Kí ló dé tí mo fi eyín mi gbé ẹran ara mi?”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “gbèjà ara mi.”
Tàbí “apẹ̀yìndà.”
Tàbí kó jẹ́, “Tí ẹnì kan bá ṣe bẹ́ẹ̀, màá dákẹ́, màá sì kú.”
Ní Héb., “Ohun méjì péré ni kí o má ṣe fún mi.”
Ní Héb., “ó,” ó ṣeé ṣe kó jẹ́ Jóòbù ló ń tọ́ka sí.
Tàbí “kòkòrò.”