Jóòbù 12:1-25

  • Jóòbù fèsì (1-25)

    • “Mi ò kéré sí yín” (3)

    • ‘Mo wá di ẹni tí wọ́n fi ń ṣe ẹlẹ́yà’ (4)

    • ‘Ọgbọ́n wà lọ́dọ̀ Ọlọ́run’ (13)

    • Ọlọ́run ga ju àwọn adájọ́ àti ọba lọ (17, 18)

12  Jóòbù wá fèsì pé:   “Ó dájú pé ẹ̀yin lẹ ní ìmọ̀,*Ọgbọ́n sì máa bá yín kú!   Àmọ́ èmi náà ní òye.* Mi ò kéré sí yín,Ta ni ò mọ àwọn nǹkan yìí?   Mo wá di ẹni tí àwọn ọ̀rẹ́ fi ń ṣe ẹlẹ́yà,+Ẹni tó ń ké pe Ọlọ́run pé kó dáhùn.+ Ẹni tó jẹ́ olódodo àti aláìlẹ́bi ni wọ́n fi ń ṣe ẹlẹ́yà.   Ẹni tí ara máa ń tù kórìíra àjálù,Ó rò pé àwọn tí ẹsẹ̀ wọn ò múlẹ̀* nìkan ló máa ń dé bá.   Àgọ́ àwọn olè wà ní àlàáfíà,+Àwọn tó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìséwu,+Àwọn tí ọlọ́run wọn wà ní ọwọ́ wọn.   Àmọ́ jọ̀ọ́, bi àwọn ẹranko, wọ́n á sì kọ́ ọ;Àti àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run, wọ́n á sì sọ fún ọ.   Tàbí kí o fiyè sí ayé,* ó sì máa kọ́ ọ;Àwọn ẹja inú òkun sì máa kéde rẹ̀ fún ọ.   Èwo nínú gbogbo àwọn yìí ni kò mọ̀Pé ọwọ́ Jèhófà ló ṣe èyí? 10  Ọwọ́ rẹ̀ ni ẹ̀mí gbogbo ohun alààyè*Àti ẹ̀mí* gbogbo èèyàn.*+ 11  Ṣebí etí máa ń dán ọ̀rọ̀ wò,Bí ahọ́n* ṣe ń tọ́ oúnjẹ wò?+ 12  Ṣebí ọ̀dọ̀ àwọn àgbà+ la ti ń rí ọgbọ́n,Ṣebí ẹ̀mí gígùn sì ń mú kéèyàn ní òye? 13  Ọgbọ́n àti agbára ńlá wà lọ́dọ̀ rẹ̀;+Ó ní ìmọ̀ràn àti òye.+ 14  Tó bá ya nǹkan lulẹ̀, kò ṣeé tún kọ́;+Tó bá ti nǹkan pa, èèyàn kankan ò lè ṣí i. 15  Tó bá dá omi dúró, ohun gbogbo á gbẹ;+Tó bá sì rán an jáde, á bo ayé.+ 16  Ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni agbára àti ọgbọ́n tó gbéṣẹ́ wà;+Òun ló ni ẹni tó ń ṣìnà àti ẹni tó ń kóni ṣìnà; 17  Ó ń mú kí àwọn agbani-nímọ̀ràn lọ láìwọ bàtà,*Ó ń sọ àwọn adájọ́ di òmùgọ̀.+ 18  Ó ń tú ìdè tí àwọn ọba fi deni,+Ó sì ń de àmùrè mọ́ ìgbáròkó wọn. 19  Ó ń mú kí àwọn àlùfáà rìn láìwọ bàtà,+Ó sì ń gbàjọba lọ́wọ́ àwọn tí wọ́n fìdí múlẹ̀ gbọn-in nípò agbára;+ 20  Ó ń pa àwọn agbani-nímọ̀ràn tí wọ́n fọkàn tán lẹ́nu mọ́,Ó sì ń gba làákàyè àwọn àgbà ọkùnrin;* 21  Ó ń rọ̀jò àbùkù sórí àwọn èèyàn pàtàkì,+Ó sì ń mú kó rẹ àwọn alágbára;* 22  Ó ń tú àwọn ohun tó jinlẹ̀ síta látinú òkùnkùn,+Ó sì ń tan ìmọ́lẹ̀ sí òkùnkùn biribiri; 23  Ó ń mú kí àwọn orílẹ̀-èdè di ńlá, kó lè pa wọ́n run;Ó ń mú kí àwọn orílẹ̀-èdè tóbi sí i, kó lè kó wọn lọ sí ìgbèkùn. 24  Ó ń gba òye* àwọn olórí àwọn èèyàn,Ó sì ń mú kí wọ́n rìn kiri ní ilẹ̀ tó ti di ahoro, tí kò sì lójú ọ̀nà.+ 25  Wọ́n ń táràrà nínú òkùnkùn,+ níbi tí kò ti sí ìmọ́lẹ̀;Ó ń mú kí wọ́n máa rìn gbéregbère bí ọ̀mùtípara.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Héb., “ẹ̀yin ni àwọn èèyàn náà.”
Ní Héb., “ọkàn.”
Tàbí “tí ẹsẹ̀ wọn ń yọ̀.”
Tàbí kó jẹ́, “bá ayé sọ̀rọ̀.”
Tàbí “ọkàn gbogbo ẹni tó wà láàyè.”
Tàbí “èémí.”
Ní Héb., “gbogbo ẹran ara èèyàn.”
Ní Héb., “òkè ẹnu.”
Tàbí “láìsí nǹkan kan lára wọn.”
Tàbí “àwọn àgbààgbà.”
Ní Héb., “tú àmùrè àwọn alágbára.”
Ní Héb., “ọkàn.”