Jóòbù 10:1-22

  • Jóòbù ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ (1-22)

    • ‘Kí ló dé tí Ọlọ́run fi ń bá mi jà?’ (2)

    • Ọlọ́run yàtọ̀ sí Jóòbù tó jẹ́ ẹni kíkú (4-12)

    • ‘Kí ara tù mí díẹ̀’ (20)

10  “Mo* kórìíra ayé mi gidigidi.+ Mi ò ní pa bó ṣe ń ṣe mi mọ́ra. Màá sọ̀rọ̀ látinú ẹ̀dùn ọkàn* tó bá mi!   Màá sọ fún Ọlọ́run pé: ‘Má ṣe dá mi lẹ́bi. Jẹ́ kí n mọ ìdí tí o fi ń bá mi jà.   Ṣé ó máa ṣe ọ́ láǹfààní tí o bá fìyà jẹni,Tí o bá kórìíra iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,+Tí o sì fara mọ́ ìmọ̀ràn àwọn ẹni burúkú?   Ṣé ojú rẹ dà bíi ti èèyàn ni,Àbí o máa ń wo nǹkan bíi ti ẹni kíkú?   Ṣé bí ọjọ́ àwọn ẹni kíkú ni àwọn ọjọ́ rẹ rí,Àbí àwọn ọdún rẹ dà bíi ti èèyàn,+   Tí o fi ń wá àṣìṣe mi, Tí o sì ń wá ẹ̀ṣẹ̀ mi?+   O mọ̀ pé mi ò jẹ̀bi,+Kò sì sí ẹni tó lè gbà mí lọ́wọ́ rẹ.+   Ọwọ́ rẹ lo fi mọ mí tí o sì fi dá mi,+Àmọ́ ní báyìí, o fẹ́ pa mí run pátápátá.   Jọ̀ọ́, rántí pé amọ̀ lo fi mọ mí,+Àmọ́ ní báyìí, o mú kí n pa dà sínú erùpẹ̀.+ 10  Ṣebí o dà mí jáde bíi wàràTí o sì mú kí n dì bíi wàràkàṣì? 11  O fi awọ àti ẹran bò mí,O sì fi egungun àti iṣan hun mí pọ̀.+ 12  O ti fún mi ní ìyè, o sì ti fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn sí mi;O ti fi ìkẹ́ rẹ dáàbò bo ẹ̀mí* mi.+ 13  Àmọ́ o gbèrò ní bòókẹ́lẹ́ láti ṣe àwọn nǹkan yìí.* Mo mọ̀ pé ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn nǹkan yìí ti wá. 14  Tí mo bá ṣẹ̀, o máa ṣọ́ mi,+O ò sì ní dá mi láre. 15  Tí mo bá jẹ̀bi, mo gbé! Tí mi ò bá tiẹ̀ mọwọ́ mẹsẹ̀, mi ò lè gbé orí mi sókè,+Torí ìtìjú àti ìyà+ ti bò mí mọ́lẹ̀. 16  Tí mo bá gbé orí mi sókè, o máa dọdẹ mi bíi ti kìnnìún,+O sì tún máa fi agbára rẹ bá mi jà. 17  O mú àwọn ẹlẹ́rìí míì wá láti ta kò mí,O sì túbọ̀ bínú sí mi, Bí mo ṣe ń tinú ìnira kan bọ́ sínú ìnira míì. 18  Torí náà, kí ló dé tí o mú mi jáde látinú ikùn?+ Ó yẹ kí n ti kú kí ojú kankan tó rí mi. 19  Ṣe ni ì bá dà bíi pé mi ò gbé ayé rí;Mi ò bá kàn ti inú ikùn lọ sí sàréè.’ 20  Ṣebí àwọn ọjọ́ mi ò pọ̀?+ Kó fi mí sílẹ̀;Kó gbé ojú rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi, kí ara lè tù mí díẹ̀*+ 21  Kí n tó lọ, tí mi ò sì ní pa dà wá,+Sí ilẹ̀ tó ṣókùnkùn biribiri,*+ 22  Sí ilẹ̀ tí ìṣúdùdù rẹ̀ pọ̀ gidigidi,Ilẹ̀ tó ṣókùnkùn biribiri, tó sì rí rúdurùdu,Níbi tí ìmọ́lẹ̀ pàápàá ti dà bí òkùnkùn.”

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “Ọkàn mi.”
Tàbí “ọgbẹ́ ọkàn.”
Tàbí “èémí; ìwàláàyè.”
Ní Héb., “O sì ti fi àwọn nǹkan yìí pa mọ́ sínú ọkàn rẹ.”
Tàbí “inú mi lè dùn díẹ̀.”
Tàbí “ilẹ̀ òkùnkùn àti òjìji ikú.”