Hósíà 12:1-14
12 “Ẹ̀fúùfù ni Éfúrémù fi ṣe oúnjẹ.
Ó sì ń sá tẹ̀ lé ẹ̀fúùfù ìlà oòrùn láti àárọ̀ ṣúlẹ̀.
Ó mú kí irọ́ àti ìwà ipá pọ̀ sí i.
Ó bá Ásíríà dá májẹ̀mú,+ ó sì gbé òróró lọ sí Íjíbítì.+
2 Jèhófà máa pe Júdà lẹ́jọ́;+Ó máa pe Jékọ́bù wá jíhìn nítorí àwọn ọ̀nà rẹ̀,Ó sì máa san án lẹ́san àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.+
3 Nígbà tó wà nínú ìyá rẹ̀, ó gbá arákùnrin rẹ̀ mú ní gìgísẹ̀,+Ó sì fi gbogbo okun rẹ̀ bá Ọlọ́run wọ̀jà.+
4 Ó bá áńgẹ́lì kan jà títí ó fi borí.
Ó sunkún, ó sì bẹ̀ ẹ́ pé kó ṣojúure sí òun.”+
Ọlọ́run rí i ní Bẹ́tẹ́lì, ibẹ̀ ni Ó sì ti bá wa sọ̀rọ̀,+
5 Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun+ ni,Jèhófà sì ni orúkọ tí a fi ń rántí rẹ̀.*+
6 “Torí náà, pa dà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ,+Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ àti ìdájọ́ òdodo bọ́ mọ́ ẹ lọ́wọ́,+Sì máa ní ìrètí nínú Ọlọ́run rẹ nígbà gbogbo.
7 Àmọ́ ọwọ́ oníṣòwò* ni òṣùwọ̀n ẹ̀tàn wà;Ó fẹ́ràn lílu jìbìtì.+
8 Éfúrémù ń sọ pé, ‘Ní tòótọ́, mo ti di ọlọ́rọ̀;+Mo ti ní ọrọ̀.+
Nínú gbogbo làálàá mi, wọn ò ní rí àìtọ́ tàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan.’
9 Ṣùgbọ́n èmi ni Jèhófà Ọlọ́run rẹ láti ilẹ̀ Íjíbítì wá.+
Màá tún mú kí o máa gbé inú àwọn àgọ́Bí ìgbà àkókò tí a ti yàn.*
10 Mo bá àwọn wòlíì sọ̀rọ̀,+Mo mú kí ìran tí wọ́n rí pọ̀ sí i,Mo sì tipasẹ̀ àwọn wòlíì ṣe àkàwé.
11 Ẹ̀tàn*+ àti àìṣòótọ́ ti wà ní Gílíádì.
Wọ́n ti fi àwọn akọ màlúù rúbọ ní Gílígálì,+Àwọn pẹpẹ wọn sì dà bí àwọn òkúta tí a tò jọ sí àárín àwọn ebè inú oko.+
12 Jékọ́bù sá lọ sí agbègbè* Árámù;*+Ísírẹ́lì+ ṣiṣẹ́ níbẹ̀ nítorí àtifẹ́ ìyàwó,+Ó sì ń da àgùntàn nítorí ìyàwó.+
13 Jèhófà tipasẹ̀ wòlíì kan mú Ísírẹ́lì jáde kúrò ní Íjíbítì,+Ó sì fi wòlíì kan ṣọ́ ọ.+
14 Éfúrémù ti dá ẹ̀ṣẹ̀ tó burú jáì;+Ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ tó ta sílẹ̀ wà lórí rẹ̀;Olúwa rẹ̀ á sì san án lẹ́san ẹ̀gàn rẹ̀.”+

