Sí Àwọn Ará Gálátíà 4:1-31

  • Ẹ kì í ṣe ẹrú mọ́, ọmọ ni yín (1-7)

  • Ọ̀rọ̀ àwọn ará Gálátíà jẹ Pọ́ọ̀lù lógún (8-20)

  • Hágárì àti Sérà: májẹ̀mú méjì (21-31)

    • Jerúsálẹ́mù ti òkè ní òmìnira, òun sì ni ìyá wa (26)

4  Ní báyìí, mo sọ pé nígbà tí ajogún náà bá ṣì jẹ́ ọmọdé, kò yàtọ̀ sí ẹrú, bó tilẹ̀ jẹ́ olúwa ohun gbogbo,  àmọ́ ó wà lábẹ́ àwọn alábòójútó àti àwọn ìríjú títí di ọjọ́ tí bàbá rẹ̀ ti yàn.  Bákan náà, ní tiwa, nígbà tí a wà lọ́mọdé, àwọn èrò àti ìṣe ayé* ń mú wa lẹ́rú.+  Àmọ́ nígbà tí àkókò tó, Ọlọ́run rán Ọmọ rẹ̀, ẹni tí obìnrin bí,+ tí ó sì wà lábẹ́ òfin,+  kí ó lè ra àwọn tó wà lábẹ́ òfin,+ kí ó sì tipa bẹ́ẹ̀ tú wọn sílẹ̀, kí a lè rí ìsọdọmọ gbà.+  Nítorí pé ẹ jẹ́ ọmọ, Ọlọ́run ti rán ẹ̀mí+ Ọmọ rẹ̀ sínú ọkàn wa,+ ó sì ń ké jáde pé: “Ábà,* Bàbá!”+  Torí náà, ẹ kì í ṣe ẹrú mọ́, ọmọ ni yín; tí ẹ bá sì jẹ́ ọmọ, ẹ tún jẹ́ ajogún nípasẹ̀ Ọlọ́run.+  Síbẹ̀, nígbà tí ẹ kò mọ Ọlọ́run, ẹ̀ ń ṣẹrú àwọn tí kì í ṣe ọlọ́run.  Àmọ́ ní báyìí tí ẹ ti mọ Ọlọ́run, tàbí ká kúkú sọ pé, tí Ọlọ́run ti mọ̀ yín, kí ló dé tí ẹ tún ń pa dà sí àwọn ohun àkọ́bẹ̀rẹ̀ tó jẹ́ aláìlera+ àti aláìníláárí,* tí ẹ sì tún fẹ́ ṣẹrú wọn?+ 10  Ẹ̀ ń pa àwọn ọjọ́ àti oṣù+ àti àsìkò àti ọdún mọ́ délẹ̀délẹ̀. 11  Ẹ̀rù ń bà mí nítorí yín, kó má lọ jẹ́ pé lásán ni gbogbo wàhálà tí mo ṣe lórí yín. 12  Ẹ̀yin ará, mo bẹ̀ yín, ẹ dà bí èmi, nítorí èmi náà ti máa ń ṣe bíi tiyín tẹ́lẹ̀.+ Ẹ ò ṣe àìtọ́ kankan sí mi. 13  Ṣùgbọ́n ẹ mọ̀ pé àìsàn tó ṣe mí ló jẹ́ kí n kọ́kọ́ láǹfààní láti kéde ìhìn rere fún yín. 14  Bó tiẹ̀ jẹ́ pé àdánwò ni àìlera mi jẹ́ fún yín, ẹ ò fojú pa mí rẹ́, ẹ ò sì kórìíra mi;* àmọ́ ṣe lẹ gbà mí bí áńgẹ́lì Ọlọ́run, bíi Kristi Jésù. 15  Ibo ni ayọ̀ tí ẹ ní tẹ́lẹ̀ wà? Nítorí mo jẹ́rìí yín pé, ká ló ṣeé ṣe ni, ẹ lè yọ ojú yín fún mi.+ 16  Ṣé mo ti wá di ọ̀tá yín torí pé mo sọ òótọ́ fún yín ni? 17  Àwọn kan ń wá ọ̀nà lójú méjèèjì láti fà yín sábẹ́ ara wọn, àmọ́ kì í ṣe fún ire yín; ṣe ni wọ́n fẹ́ fà yín kúrò lọ́dọ̀ mi, kó lè máa yá yín lára láti tẹ̀ lé wọn. 18  Síbẹ̀, ó dáa tí ẹnì kan bá ń wá yín lójú méjèèjì fún ire yín, tí kì í ṣe nígbà tí mo bá wà lọ́dọ̀ yín nìkan, 19  ẹ̀yin ọmọ mi kéékèèké,+ tí mo tún tìtorí yín wà nínú ìrora ìbímọ títí ẹ ó fi lè gbé Kristi yọ* nínú yín. 20  Ó wù mí kí n wà lọ́dọ̀ yín ní báyìí, kí n sì sọ̀rọ̀ lọ́nà tó yàtọ̀, torí ọkàn mi ń dààmú nítorí yín. 21  Ẹ sọ fún mi, ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ wà lábẹ́ òfin, Ṣé ẹ ò gbọ́ ohun tí Òfin sọ ni? 22  Bí àpẹẹrẹ, ó wà lákọsílẹ̀ pé Ábúráhámù ní ọmọkùnrin méjì, ọ̀kan látọ̀dọ̀ ìránṣẹ́bìnrin,+ èkejì látọ̀dọ̀ obìnrin tó lómìnira;+ 23  àmọ́ èyí tí ìránṣẹ́bìnrin bí jẹ́ lọ́nà ti ẹ̀dá,*+ èyí tí obìnrin tó lómìnira sì bí jẹ́ nípasẹ̀ ìlérí.+ 24  A lè fi àwọn nǹkan yìí ṣe àkàwé; àwọn obìnrin yìí dúró fún májẹ̀mú méjì, èyí tó wá láti Òkè Sínáì,+ tó ń bí ọmọ fún ìsìnrú, ni Hágárì. 25  Hágárì dúró fún Sínáì,+ òkè kan ní Arébíà, ó sì ṣe rẹ́gí pẹ̀lú Jerúsálẹ́mù ti òní, torí ó ń ṣẹrú pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀. 26  Àmọ́ Jerúsálẹ́mù ti òkè ní òmìnira, òun sì ni ìyá wa. 27  Nítorí ó wà lákọsílẹ̀ pé: “Máa yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀, ìwọ àgàn tí kò bímọ; bú sígbe ayọ̀, ìwọ obìnrin tí kò ní ìrora ìbímọ; nítorí àwọn ọmọ obìnrin tó ti di ahoro pọ̀ ju ti obìnrin tó ní ọkọ lọ.”+ 28  Tóò, ẹ̀yin ará, ẹ̀yin náà jẹ́ ọmọ ìlérí bí Ísákì ṣe jẹ́.+ 29  Àmọ́ bó ṣe rí nígbà yẹn tí èyí tí a bí lọ́nà ti ẹ̀dá* bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe inúnibíni sí èyí tí a bí lọ́nà ti ẹ̀mí,+ bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe rí ní báyìí.+ 30  Síbẹ̀, kí ni ìwé mímọ́ sọ? “Lé ìránṣẹ́bìnrin náà àti ọmọkùnrin rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ìránṣẹ́bìnrin náà kò ní bá ọmọ obìnrin tó lómìnira pín ogún lọ́nàkọnà.”+ 31  Nítorí náà, ẹ̀yin ará, a kì í ṣe ọmọ ìránṣẹ́bìnrin, ọmọ obìnrin tó lómìnira ni wá.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “àwọn ohun àkọ́bẹ̀rẹ̀ ayé.”
Ọ̀rọ̀ Hébérù tàbí Árámáíkì tó túmọ̀ sí “Bàbá!”
Tàbí “akúrẹtẹ̀.”
Tàbí “tutọ́ sí mi lára.”
Tàbí “títí Kristi yóò fi di odindi.”
Ní Grk., “ara.”
Ní Grk., “ara.”