Kíróníkà Kejì 16:1-14

  • Àdéhùn tí Ásà bá Síríà ṣe (1-6)

  • Hánáánì bá Ásà wí (7-10)

  • Ikú Ásà (11-14)

16  Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Ásà, Bááṣà+ ọba Ísírẹ́lì wá dojú kọ Júdà, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́* Rámà,+ kí ẹnikẹ́ni má bàa jáde tàbí kí ó wọlé sọ́dọ̀* Ásà ọba Júdà.+  Ni Ásà bá kó fàdákà àti wúrà jáde látinú àwọn ibi ìṣúra ilé Jèhófà+ àti ilé* ọba, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Bẹni-hádádì ọba Síríà+ tó ń gbé ní Damásíkù, ó sọ pé:  “Àdéhùn* kan wà láàárín èmi àti ìwọ àti láàárín bàbá mi àti bàbá rẹ. Mo fi fàdákà àti wúrà ránṣẹ́ sí ọ. Wò ó, lọ yẹ àdéhùn* tí o bá Bááṣà ọba Ísírẹ́lì ṣe, kó lè pa dà lẹ́yìn mi.”  Bẹni-hádádì ṣe ohun tí Ọba Ásà sọ, ó rán àwọn olórí ọmọ ogun rẹ̀ láti gbéjà ko àwọn ìlú Ísírẹ́lì, wọ́n sì ṣá Íjónì,+ Dánì + àti Ebẹli-máímù balẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ibi tí wọ́n ń kó nǹkan pa mọ́ sí ní àwọn ìlú Náfútálì.+  Nígbà tí Bááṣà gbọ́ ohun tó ṣẹlẹ̀, ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ló jáwọ́ nínú kíkọ́* Rámà, ó sì pa iṣẹ́ tó ń ṣe níbẹ̀ tì.  Ọba Ásà wá kó gbogbo Júdà jọ, wọ́n kó àwọn òkúta àti ẹ̀là gẹdú tó wà ní Rámà,+ tí Bááṣà fi ń kọ́lé,+ ó sì fi wọ́n kọ́* Gébà+ àti Mísípà.+  Ní àkókò yẹn, Hánáánì+ aríran wá bá Ásà ọba Júdà, ó sì sọ fún un pé: “Nítorí o gbẹ́kẹ̀ lé* ọba Síríà, tí o kò sì gbẹ́kẹ̀ lé* Jèhófà Ọlọ́run rẹ, àwọn ọmọ ogun ọba Síríà ti bọ́ mọ́ ẹ lọ́wọ́.+  Ṣebí àwọn ará Etiópíà àti àwọn ará Líbíà ní àwọn ọmọ ogun tó pọ̀ rẹpẹtẹ àti àwọn kẹ̀kẹ́ ẹṣin pẹ̀lú àwọn agẹṣin? Àmọ́ torí pé o gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà, ó fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́.+  Nítorí ojú Jèhófà ń lọ káàkiri gbogbo ayé+ láti fi agbára* rẹ̀ hàn nítorí àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sìn ín.+ O ti hùwà òmùgọ̀ lórí ọ̀ràn yìí; láti ìsinsìnyí lọ, ogun yóò máa jà ọ́.”+ 10  Àmọ́, inú bí Ásà sí aríran náà, ó sì fi í sẹ́wọ̀n,* torí ohun tó sọ mú kí Ásà gbaná jẹ. Ní àkókò yẹn kan náà, Ásà bẹ̀rẹ̀ sí í fìyà jẹ àwọn kan lára àwọn èèyàn náà. 11  Ní ti ìtàn Ásà, láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin, ó wà lákọsílẹ̀ nínú Ìwé Àwọn Ọba Júdà àti ti Ísírẹ́lì.+ 12  Ní ọdún kọkàndínlógójì ìjọba Ásà, àrùn kan mú un ní ẹsẹ̀, ó sì di àìsàn ńlá sí i lára; síbẹ̀ nínú àìsàn tó wà, kò yíjú sí Jèhófà, àwọn oníṣègùn ló yíjú sí. 13  Níkẹyìn, Ásà sinmi pẹ̀lú àwọn baba ńlá rẹ̀;+ ó kú ní ọdún kọkànlélógójì ìjọba rẹ̀. 14  Nítorí náà, wọ́n sin ín sí ibi ìsìnkú rẹ̀ tó lọ́lá, èyí tó gbẹ́ fún ara rẹ̀ sí Ìlú Dáfídì;+ wọ́n sì tẹ́ ẹ sórí àga ìgbókùú tí wọ́n ti fi òróró básámù sí lára àti oríṣiríṣi èròjà tí a pò mọ́ àkànṣe òróró ìpara.+ Síwájú sí i, wọ́n ṣe ìfinásun* tó ṣàrà ọ̀tọ̀ nítorí rẹ̀ nígbà ìsìnkú rẹ̀.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “sí ìpínlẹ̀.”
Tàbí “mọ odi; tún Rámà kọ́.”
Tàbí “ààfin.”
Tàbí “Májẹ̀mú.”
Tàbí “májẹ̀mú.”
Tàbí “mímọ odi; títún Rámà kọ́.”
Tàbí “mọ odi; tún Gébà kọ́.”
Ní Héb., “gbára lé.”
Ní Héb., “gbára lé.”
Tàbí “ìtìlẹ́yìn.”
Ní Héb., “sí ilé àbà.”
Ó ṣe kedere pé, wọn ò finá sun òkú Ásà, àwọn èròjà ni wọ́n finá sun.