Òwe 13:1-25

  • Àwọn tó ń wá ìmọ̀ràn máa ń gbọ́n (10)

  • Ìrètí pípẹ́ máa ń mú ọkàn ṣàìsàn (12)

  • Aṣojú tó jẹ́ olóòótọ́ ń mú ìwòsàn wá (17)

  • Ẹni tó ń bá ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́n (20)

  • Ọ̀nà kan tí a lè gbà fìfẹ́ hàn ni pé ká báni wí (24)

13  Ọlọ́gbọ́n ọmọ máa ń gba ẹ̀kọ́ bàbá rẹ̀,+Àmọ́ ẹlẹ́gàn kì í fetí sí ìbáwí.*+   Ọ̀rọ̀ ẹnu èèyàn máa jẹ́ kó rí ohun rere gbà,+Àmọ́ ìfẹ́ ọkàn àwọn oníbékebèke máa ń jẹ́ kí wọ́n hùwà ipá.   Ẹni tó ń ṣọ́ ẹnu rẹ̀* ń dáàbò bo ẹ̀mí* rẹ̀,+Àmọ́ ẹni tó ń la ẹnu rẹ̀ gbàgà yóò pa run.+   Ọ̀pọ̀ nǹkan ni ọ̀lẹ ń fẹ́, síbẹ̀ kò* ní nǹkan kan,+Àmọ́ ẹni* tó ń ṣiṣẹ́ kára yóò ní ànító.*+   Olódodo kórìíra irọ́,+Àmọ́ ìwà ẹni burúkú ń fa ìtìjú àti àbùkù.   Òdodo ń dáàbò bo ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ tọ́,+Àmọ́ ìwà burúkú máa ń dojú ẹlẹ́ṣẹ̀ dé.   Ẹnì kan wà tó ń ṣe bíi pé òun jẹ́ ọlọ́rọ̀, síbẹ̀ kò ní nǹkan kan;+Ẹlòmíì sì wà tó ń ṣe bíi pé aláìní lòun, síbẹ̀ ó ní ọrọ̀ rẹpẹtẹ.   Ọrọ̀ ni ọlọ́rọ̀ fi ń ra ẹ̀mí* rẹ̀ pa dà,+Àmọ́ ẹnikẹ́ni kì í halẹ̀ mọ́ aláìní.*+   Ìmọ́lẹ̀ àwọn olódodo mọ́lẹ̀ rekete,*+Àmọ́ fìtílà àwọn ẹni burúkú ni a ó pa.+ 10  Wàhálà ni ìkọjá àyè máa ń dá sílẹ̀,+Àmọ́ ọgbọ́n jẹ́ ti àwọn tó ń wá ìmọ̀ràn.*+ 11  Ọrọ̀ tí èèyàn fi ìkánjú kó jọ* kì í pẹ́ tán,+Àmọ́ ọrọ̀ tí èèyàn ń kó jọ díẹ̀díẹ̀* á máa pọ̀ sí i. 12  Ìrètí* pípẹ́ máa ń mú ọkàn ṣàìsàn,+Àmọ́ nígbà tí ìfẹ́ ọkàn ẹni bá ṣẹ, igi ìyè ni.+ 13  Ẹni tí kò bá ka ìtọ́ni* sí á jìyà rẹ̀,+Àmọ́ ẹni tó bá bọ̀wọ̀ fún àṣẹ yóò gba èrè rẹ̀.+ 14  Ẹ̀kọ́* ọlọgbọ́n jẹ́ orísun ìyè+Kì í jẹ́ kéèyàn kó sínú ìdẹkùn ikú. 15  Ìjìnlẹ̀ òye ń mú kéèyàn jèrè ojú rere,Àmọ́ ọ̀nà àwọn oníbékebèke korò. 16  Aláròjinlẹ̀ máa ń fi ìmọ̀ hùwà,+Àmọ́ òmùgọ̀ máa ń fi ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ hàn.+ 17  Òjíṣẹ́ burúkú máa ń kó sínú ìjàngbọ̀n,+Àmọ́ aṣojú tó jẹ́ olóòótọ́ ń mú ìwòsàn wá.+ 18  Ẹni tí kò bá ka ìbáwí sí á di òtòṣì, á sì kan àbùkù,Àmọ́ ẹni tó bá ń gba ìtọ́sọ́nà* ni a ó gbé ga.+ 19  Nígbà tí ìfẹ́ ọkàn ẹni bá ṣẹ, ó máa ń dùn mọ́ni,*+Àmọ́ òmùgọ̀ kì í fẹ́ jáwọ́ nínú ìwà burúkú.+ 20  Ẹni tó ń bá ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́n,+Àmọ́ ẹni tó ń bá òmùgọ̀ da nǹkan pọ̀ yóò rí láburú.+ 21  Àjálù kì í dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,+Àmọ́ aásìkí ni èrè àwọn olódodo.+ 22  Ẹni rere máa ń fi ogún sílẹ̀ fún àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀,Àmọ́ ọrọ̀ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó kó jọ fún àwọn olódodo.+ 23  Ọ̀pọ̀ oúnjẹ ló ń jáde látinú oko tí àwọn aláìní dá,Àmọ́ àìsí ìdájọ́ òdodo lè gbá a* lọ. 24  Ẹni tó bá fa ọ̀pá* sẹ́yìn kórìíra ọmọ rẹ̀,+Àmọ́ ẹni tó bá nífẹ̀ẹ́ ọmọ rẹ̀ máa ń bá a wí dáadáa.*+ 25  Olódodo ń jẹ àjẹtẹ́rùn,*+Àmọ́ inú àwọn ẹni burúkú ṣófo.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ìtọ́sọ́nà.”
Tàbí “ohun tó ń sọ.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ọkàn rẹ̀ kò.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “ni a ó mú sanra.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “aláìní kì í gbọ́ ìbáwí.”
Ní Héb., “ń yọ̀.”
Tàbí “fèrò wérò.”
Tàbí “Ọrọ̀ tó wá látinú asán.”
Ní Héb., “ń fi ọwọ́ kó jọ.”
Tàbí “Ìfojúsọ́nà.”
Tàbí “ọ̀rọ̀.”
Tàbí “Òfin.”
Tàbí “ìbáwí.”
Tàbí “mọ́ ọkàn.”
Tàbí “aláìní.”
Tàbí “ìbáwí; ìfìyàjẹni.”
Tàbí kó jẹ́, “kánmọ́kánmọ́.”
Tàbí “Olódodo ń jẹ, ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn.”