Òwe 11:1-31

  • Ọgbọ́n wà lọ́dọ̀ àwọn tó mọ̀wọ̀n ara wọn (2)

  • Apẹ̀yìndà máa ń fa ìparun bá àwọn ẹlòmíì (9)

  • “Nípasẹ̀ ọ̀pọ̀ agbani-nímọ̀ràn, àṣeyọrí á wà” (14)

  • Ẹni tó bá láwọ máa láásìkí (25)

  • Ẹni tó bá gbẹ́kẹ̀ lé ọrọ̀ rẹ̀ máa ṣubú (28)

11  Òṣùwọ̀n èké* jẹ́ ohun ìríra lójú Jèhófà,Àmọ́ ìwọ̀n* tí ó pé máa ń mú inú rẹ̀ dùn.+   Tí ìkọjá àyè bá dé, àbùkù á tẹ̀ lé e,+Àmọ́ ọgbọ́n wà lọ́dọ̀ àwọn tí wọ́n mọ̀wọ̀n ara wọn.+   Ìwà títọ́ àwọn adúróṣinṣin ló ń tọ́ wọn sọ́nà,+Àmọ́ ẹ̀tàn àwọn oníbékebèke ni yóò pa wọ́n run.+   Ọrọ̀* kò ní ṣeni láǹfààní ní ọjọ́ ìbínú ńlá,+Àmọ́ òdodo ló ń gbani lọ́wọ́ ikú.+   Òdodo aláìlẹ́bi ń mú kí ipa ọ̀nà rẹ̀ tọ́,Àmọ́ ẹni burúkú á ṣubú nítorí ìwà burúkú rẹ̀.+   Òdodo àwọn adúróṣinṣin ni yóò gbà wọ́n,+Àmọ́ ìfẹ́ ọkàn àwọn oníbékebèke ni yóò dẹkùn mú wọn.+   Nígbà tí ẹni burúkú bá kú, ìrètí rẹ̀ á ṣègbé;Ohun tó sì ń retí pé òun á fi agbára òun ṣe yóò ṣègbé pẹ̀lú.+   A gba olódodo lọ́wọ́ wàhálà,Ẹni burúkú sì bọ́ síbẹ̀ dípò rẹ̀.+   Ẹnu ni apẹ̀yìndà* fi ń fa ìparun bá ọmọnìkejì rẹ̀,Àmọ́ ìmọ̀ ló ń gba àwọn olódodo sílẹ̀.+ 10  Ìwà rere àwọn olódodo ń mú kí ìlú yọ̀,Nígbà tí àwọn ẹni burúkú bá ṣègbé, igbe ìdùnnú á ta.+ 11  Nítorí ìbùkún àwọn adúróṣinṣin, ìlú á ní ìgbéga,+Àmọ́ ẹnu àwọn ẹni burúkú á wó o lulẹ̀.+ 12  Ẹni tí kò ní làákàyè* ń kórìíra* ọmọnìkejì rẹ̀,Àmọ́ ẹni tó ní ìjìnlẹ̀ òye máa ń dákẹ́.+ 13  Abanijẹ́ ń sọ ọ̀rọ̀ àṣírí kiri,+Àmọ́ ẹni tó ṣeé fọkàn tán* máa ń pa àṣírí mọ́.* 14  Nígbà tí kò bá sí ìtọ́sọ́nà ọlọgbọ́n, àwọn èèyàn á ṣubú,Àmọ́ nípasẹ̀ ọ̀pọ̀ agbani-nímọ̀ràn,* àṣeyọrí* á wà.+ 15  Ẹni tó bá ṣe onídùúró* fún àjèjì yóò rí láburú,+Àmọ́ ẹni tó bá yẹra fún* bíbọ ọwọ́ nínú ẹ̀jẹ́ yóò rí ààbò. 16  Obìnrin onínúure* ń gba ògo,+Àmọ́ àwọn ìkà èèyàn ń gbẹ́sẹ̀ lé ọrọ̀. 17  Ẹni tó ń ṣoore* ń ṣe ara rẹ̀ láǹfààní,*+Àmọ́ ìkà èèyàn ń fa wàhálà* bá ara rẹ̀.+ 18  Ẹni burúkú ń jẹ èrè asán,+Àmọ́ ẹni tó ń gbin òdodo ń jẹ èrè gidi.+ 19  Ẹni tó dúró gbọn-in lórí òdodo máa rí ìyè,+Àmọ́ ẹni tó ń lépa ohun búburú á rí ikú he. 20  Àwọn tí ọkàn wọn burú jẹ́ ohun ìríra lójú Jèhófà,+Àmọ́ àwọn tí ọ̀nà wọn tọ́ ń mú inú rẹ̀ dùn.+ 21  Jẹ́ kó dá ọ lójú pé:* Ẹni ibi kò ní lọ láìjìyà,+Àmọ́ àwọn ọmọ olódodo yóò yè bọ́. 22  Bí òrùka wúrà ní imú ẹlẹ́dẹ̀Ni obìnrin tó rẹwà àmọ́ tí kì í lo làákàyè. 23  Ìfẹ́ ọkàn àwọn olódodo ń yọrí sí ire,+Àmọ́ ohun tí àwọn ẹni burúkú ń retí máa ń yọrí sí ìbínú ńlá. 24  Ẹnì kan wà tó ń fúnni lọ́pọ̀lọpọ̀,* ó sì ń ní sí i;+Ẹnì kan sì wà tó ń fawọ́ ohun tó yẹ kó fúnni sẹ́yìn, àmọ́ ó di aláìní.+ 25  Ẹni* tó bá lawọ́ máa láásìkí,*+Ẹni tó bá sì ń mára tu àwọn míì,* ara máa tu òun náà.+ 26  Àwọn èèyàn á gégùn-ún fún ẹni tó bá kó oúnjẹ pa mọ́,Àmọ́ wọ́n á súre fún ẹni tó bá ń tà á. 27  Ẹni tó ń wá bó ṣe máa ṣe rere lójú méjèèjì ń wá ojú rere,+Àmọ́ ẹni tó bá ń wá ibi, ó dájú pé ibi ló máa wá sórí rẹ̀.+ 28  Ẹni tó bá gbẹ́kẹ̀ lé ọrọ̀ rẹ̀ máa ṣubú,+Àmọ́ olódodo máa rú yọ bí ewé tútù.+ 29  Ẹni tó bá ń fa wàhálà* bá agbo ilé rẹ̀ á jogún òfo,*+Òmùgọ̀ èèyàn ló sì máa jẹ́ ìránṣẹ́ ọlọ́gbọ́n. 30  Èso olódodo jẹ́ igi ìyè,+Ẹni tó bá sì ń jèrè ọkàn* jẹ́ ọlọ́gbọ́n.+ 31  Tó bá jẹ́ pé ẹ̀san wà fún olódodo lóòótọ́,Mélòómélòó ni ti ẹni burúkú àti ẹlẹ́ṣẹ̀!+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “òkúta ìwọ̀n.”
Tàbí “ìrẹ́nijẹ.”
Tàbí “Àwọn ohun iyebíye.”
Tàbí “ẹni tí kò gba Ọlọ́run gbọ́.”
Ní Héb., “tí ọkàn kù fún.”
Tàbí “pẹ̀gàn.”
Ní Héb., “olóòótọ́ ní ẹ̀mí.”
Ní Héb., “bo ọ̀rọ̀ mọ́lẹ̀.”
Tàbí “olùdámọ̀ràn.”
Tàbí “ìgbàlà.”
Tàbí “onígbọ̀wọ́.”
Ní Héb., “kórìíra.”
Tàbí “tó rẹwà.”
Tàbí “Ẹni tó ní ìfẹ́ tí kì í yẹ̀.”
Tàbí “ń ṣe ọkàn rẹ̀ lóore.”
Tàbí “ìtìjú.”
Ní Héb., “Ọwọ́ sí ọwọ́.”
Ní Héb., “tó ń fọ́n ká.”
Tàbí “Ọkàn.”
Ní Héb., “ni a ó mú sanra.”
Ní Héb., “bomi rin àwọn míì fàlàlà.”
Tàbí “kó ìtìjú.”
Ní Héb., “ẹ̀fúùfù.”