Òwe 10:1-32

  • Ọlọ́gbọ́n ọmọ ń mú inú bàbá rẹ̀ dùn (1)

  • Ọwọ́ tó ń ṣiṣẹ́ kára ń sọni di ọlọ́rọ̀ (4)

  • Tí ọ̀rọ̀ bá ti pọ̀, àṣìṣe kò ní ṣàì wáyé (19)

  • Ìbùkún Jèhófà ló ń sọni di ọlọ́rọ̀ (22)

  • Ìbẹ̀rù Jèhófà ń mú kí ẹ̀mí ẹni gùn (27)

10  Òwe Sólómọ́nì.+ Ọlọ́gbọ́n ọmọ ń mú inú bàbá rẹ̀ dùn,+Àmọ́ òmùgọ̀ ọmọ ń kó ẹ̀dùn ọkàn bá ìyá rẹ̀.   Àwọn ìṣúra téèyàn fi ìwà ìkà kó jọ kò ní ṣe é láǹfààní,Àmọ́ òdodo ló ń gbani lọ́wọ́ ikú.+   Jèhófà ò ní jẹ́ kí ebi pa olódodo,*+Bẹ́ẹ̀ sì ni kò ní jẹ́ kí ọwọ́ àwọn ẹni burúkú tẹ ohun tí wọ́n ń fẹ́.   Ọwọ́ tó dilẹ̀ ń sọni di òtòṣì,+Àmọ́ ọwọ́ tó ń ṣiṣẹ́ kára ń sọni di ọlọ́rọ̀.+   Ọmọ tó ní ìjìnlẹ̀ òye ń kó irè oko jọ ní ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn,Àmọ́ ọmọ tó ń dójú tini ń sùn fọnfọn nígbà ìkórè.+   Ìbùkún wà lórí olódodo,+Àmọ́ ẹnu ẹni burúkú ń bo ìwà ipá mọ́lẹ̀.   Ìrántí* olódodo yẹ fún ìbùkún,+Àmọ́ orúkọ àwọn ẹni burúkú yóò jẹrà.+   Ọlọ́gbọ́n ọkàn yóò gba ẹ̀kọ́,*+Àmọ́ ẹni tó ń sọ̀rọ̀ òmùgọ̀ ni a ó tẹ̀ mọ́lẹ̀.+   Ẹni tó ń rìn nínú ìwà títọ́ yóò máa rìn nínú ààbò,+Àmọ́ àṣírí ẹni tó ń sọ ọ̀nà ara rẹ̀ di wíwọ́ yóò tú.+ 10  Ẹni tó ń dínjú ń fa ẹ̀dùn ọkàn,+Ẹni tó sì ń sọ̀rọ̀ òmùgọ̀ ni a ó tẹ̀ mọ́lẹ̀.+ 11  Ẹnu olódodo jẹ́ orísun ìyè,+Àmọ́ ẹnu ẹni burúkú ń bo ìwà ipá mọ́lẹ̀.+ 12  Ìkórìíra ló ń dá awuyewuye sílẹ̀,Àmọ́ ìfẹ́ máa ń bo gbogbo àṣìṣe mọ́lẹ̀.+ 13  Ọgbọ́n wà ní ètè olóye,+Àmọ́ ọ̀pá wà fún ẹ̀yìn ẹni tí kò ní làákàyè.*+ 14  Àwọn ọlọ́gbọ́n máa ń fi ìmọ̀ ṣe ìṣúra,+Àmọ́ ẹnu àwọn òmùgọ̀ máa ń fa ìparun.+ 15  Ohun ìní* ọlọ́rọ̀ ni ìlú olódi rẹ̀. Ipò òṣì àwọn aláìní ni ìparun wọn.+ 16  Iṣẹ́ olódodo ń yọrí sí ìyè;Àmọ́ iṣẹ́ ọwọ́ ẹni burúkú ń yọrí sí ẹ̀ṣẹ̀.+ 17  Ẹni tó ń gba ìbáwí jẹ́* ipa ọ̀nà ìyè fún àwọn èèyàn,Àmọ́ ẹni tó ń kọ ìbáwí ń kó àwọn èèyàn ṣìnà. 18  Ẹni tó ń bo ìkórìíra rẹ̀ mọ́ra ń parọ́,+Ẹni tó sì ń tan ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́* ká jẹ́ òmùgọ̀. 19  Tí ọ̀rọ̀ bá ti pọ̀, àṣìṣe ò ní ṣàì wáyé,+Àmọ́ ẹni tó bá ń ṣọ́ ẹnu rẹ̀ á máa fi ọgbọ́n hùwà.+ 20  Ahọ́n olódodo dà bíi fàdákà tó dára jù lọ,+Àmọ́ ọkàn ẹni burúkú kò fi bẹ́ẹ̀ já mọ́ nǹkan kan. 21  Ẹnu olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèyàn,*+Àmọ́ àwọn òmùgọ̀ ń kú nítorí wọn kò ní làákàyè.+ 22  Ìbùkún Jèhófà ló ń sọni di ọlọ́rọ̀,+Kì í sì í fi ìrora* kún un. 23  Híhùwà àìnítìjú dà bí eré lójú òmùgọ̀,Àmọ́ ọgbọ́n wà fún ẹni tó ní òye.+ 24  Ohun tí ẹni burúkú ń bẹ̀rù yóò ṣẹlẹ̀ sí i;Àmọ́ a ó ṣe ohun tí ọkàn àwọn olódodo fẹ́ fún wọn.+ 25  Nígbà tí ẹ̀fúùfù bá fẹ́ kọjá, ẹni burúkú kò ní sí mọ́,+Àmọ́ olódodo jẹ́ ìpìlẹ̀ títí láé.+ 26  Bí ọtí kíkan ṣe ń ṣe eyín àti bí èéfín ṣe ń ṣe ojú,Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ ṣe rí sí ẹni tó rán an níṣẹ́.* 27  Ìbẹ̀rù Jèhófà ń mú kí ẹ̀mí ẹni gùn,+Àmọ́ ọdún àwọn ẹni burúkú ni a ó gé kúrú.+ 28  Ìfojúsọ́nà* àwọn olódodo ń mú ayọ̀ wá,+Àmọ́ ìrètí àwọn ẹni burúkú yóò ṣègbé.+ 29  Ọ̀nà Jèhófà jẹ́ ibi ààbò fún aláìlẹ́bi,+Àmọ́ ìparun ló jẹ́ fún àwọn aṣebi.+ 30  Kò sí ohun tó máa mú kí àwọn olódodo ṣubú,+Àmọ́ àwọn ẹni burúkú ò ní gbé ilẹ̀ ayé mọ́.+ 31  Ẹnu olódodo ń mú* ọgbọ́n jáde,Àmọ́, ahọ́n àyídáyidà ni a ó gé kúrò. 32  Ètè olódodo mọ ohun tó tọ́ láti sọ,Àmọ́ ẹnu ẹni burúkú jẹ́ ẹ̀tàn.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ọkàn olódodo.”
Tàbí “Orúkọ.”
Ní Héb., “àṣẹ.”
Ní Héb., “tí ọkàn kù fún.”
Tàbí “Ohun iyebíye.”
Tàbí kó jẹ́, “wà ní.”
Tàbí “àhesọ ọ̀rọ̀.”
Tàbí “tọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèyàn sọ́nà.”
Tàbí “ìbànújẹ́; ìṣòro.”
Tàbí “ẹni tó gbà á síṣẹ́.”
Tàbí “Ìrètí.”
Tàbí “so èso.”