Émọ́sì 2:1-16

  • Ìdájọ́ lórí ìdìtẹ̀ tó ń wáyé (1-16)

    • Móábù (1-3), Júdà (4, 5), Ísírẹ́lì (6-16)

2  “Ohun tí Jèhófà sọ nìyí,‘“Nítorí ìdìtẹ̀* mẹ́ta Móábù+ àti nítorí mẹ́rin, mi ò ní yí ọwọ́ mi pa dà,Nítorí pé ó jó egungun ọba Édómù láti fi ṣe ẹfun.   Torí náà, màá rán iná sí Móábù,Á sì jó àwọn ilé gogoro tó láàbò ti Kíríọ́tì+ run;Móábù á kú sínú ariwo,Nígbà tí ariwo bá sọ nítorí ogun, tí ìró ìwo sì dún.+   Màá mú alákòóso* kúrò ní àárín MóábùMàá sì pa gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ pẹ̀lú alákòóso rẹ̀,”+ ni Jèhófà wí.’   Ohun tí Jèhófà sọ nìyí,‘Nítorí ìdìtẹ̀ mẹ́ta Júdà+ àti nítorí mẹ́rin, mi ò ní yí ọwọ́ mi pa dà,Nítorí pé wọn kò tẹ̀ lé òfin* Jèhófà Àti nítorí pé wọn kò pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́;+Irọ́ tí àwọn baba ńlá wọn tọ̀ lẹ́yìn ti mú kí wọ́n ṣìnà.+   Torí náà, màá rán iná sí Júdà,Á sì jó àwọn ilé gogoro tó láàbò ní Jerúsálẹ́mù run.’+   Ohun tí Jèhófà sọ nìyí,‘Nítorí ìdìtẹ̀ mẹ́ta Ísírẹ́lì+ àti nítorí mẹ́rin, mi ò ní yí ọwọ́ mi pa dà,Torí wọ́n ta olódodo nítorí fàdákàÀti tálákà nítorí iye owó bàtà ẹsẹ̀ méjì.+   Wọ́n tẹ orí àwọn ẹni rírẹlẹ̀ mọ́ eruku ilẹ̀,+Wọ́n sì dí ọ̀nà àwọn oníwà pẹ̀lẹ́.+ Ọkùnrin kan àti bàbá rẹ̀ bá ọmọbìnrin kan náà ní àṣepọ̀,Wọ́n sì ń sọ orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́.   Orí àwọn ẹ̀wù tí wọ́n gbà láti fi ṣe ìdúró*+ ni wọ́n ń sùn gbalaja sí lẹ́gbẹ̀ẹ́ gbogbo pẹpẹ;+Owó ìtanràn tí wọ́n gbà ni wọ́n fi ra wáìnì tí wọ́n ń mu ní ilé* àwọn ọlọ́run wọn.’   ‘Ṣùgbọ́n èmi ni mo pa Ámórì rẹ́ ní ìṣojú wọn,+Ẹni tó ga bí igi kédárì, tó sì ní agbára bí àwọn igi ràgàjì;*Mo pa èso rẹ̀ run lókè àti gbòǹgbò rẹ̀ nísàlẹ̀.+ 10  Mo mú yín kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì,+Ogójì (40) ọdún ni mo fi mú yín la aginjù já,+Kí ẹ lè gba ilẹ̀ Ámórì. 11  Mo yan àwọn kan lára àwọn ọmọkùnrin yín láti jẹ́ wòlíì+Àti lára àwọn ọ̀dọ́kùnrin yín láti jẹ́ Násírì.+ Àbí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀yin ọmọ Ísírẹ́lì?’ ni Jèhófà wí. 12  ‘Àmọ́, ẹ̀ ń fún Násírì ní wáìnì mu,+Ẹ sì ń pàṣẹ fún àwọn wòlíì pé: “Ẹ kò gbọ́dọ̀ sọ tẹ́lẹ̀.”+ 13  Nítorí náà, màá tẹ̀ yín rẹ́ ní ibùgbé yín,Bíi kẹ̀kẹ́ tó kó ọkà gígé ṣe ń tẹ ohun tó wà lábẹ́ rẹ̀ ní àtẹ̀rẹ́. 14  Asáré tete kò ní rí ibi sá sí,+Alágbára kò ní lókun mọ́,Kò sì ní sí jagunjagun tó máa lè gba ẹ̀mí* ara rẹ̀ là. 15  Tafàtafà kò ní lè dúró,Asáré tete kò ní lè sá àsálà,Bẹ́ẹ̀ ni, agẹṣin kò ní lè gba ẹ̀mí* ara rẹ̀ là. 16  Kódà akíkanjú* lára àwọn jagunjagunMáa sá lọ ní ìhòòhò ní ọjọ́ yẹn,’+ ni Jèhófà wí.”

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ìwà ọ̀daràn.”
Ní Héb., “onídàájọ́.”
Tàbí “ìtọ́ni.”
Tàbí “tẹ́ńpìlì.”
Tàbí “ìdógò.”
Tàbí “igi óákù.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ẹni tí ọkàn rẹ̀ le.”