Ẹ́kísódù 4:1-31
4 Àmọ́ Mósè fèsì pé: “Tí wọn ò bá gbà mí gbọ́ ńkọ́, tí wọn ò sì fetí sí mi?+ Torí wọ́n á sọ pé, ‘Jèhófà ò fara hàn ọ́.’”
2 Jèhófà bi í pé: “Kí ló wà lọ́wọ́ rẹ yẹn?” Ó fèsì pé: “Ọ̀pá ni.”
3 Ọlọ́run sọ pé: “Jù ú sílẹ̀.” Ó jù ú sílẹ̀, ló bá di ejò;+ Mósè sì sá fún un.
4 Jèhófà sọ fún Mósè pé: “Na ọwọ́ mú un níbi ìrù.” Ó nawọ́ mú un, ó sì di ọ̀pá lọ́wọ́ rẹ̀.
5 Ọlọ́run wá sọ pé, “Èyí á jẹ́ kí wọ́n gbà gbọ́ pé Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá wọn, Ọlọ́run Ábúráhámù, Ọlọ́run Ísákì àti Ọlọ́run Jékọ́bù+ ti fara hàn ọ́.”+
6 Jèhófà tún sọ fún un pé: “Jọ̀ọ́, ki ọwọ́ rẹ bọ inú aṣọ rẹ lápá òkè.” Ó wá ki ọwọ́ bọ inú aṣọ rẹ̀. Nígbà tó yọ ọ́ jáde, ẹ̀tẹ̀ ti bò ó lọ́wọ́, ó sì funfun bíi yìnyín!+
7 Ọlọ́run wá sọ pé: “Dá ọwọ́ rẹ pa dà sínú aṣọ rẹ lápá òkè.” Ó sì dá ọwọ́ rẹ̀ pa dà sínú aṣọ rẹ̀. Nígbà tó yọ ọ́ jáde nínú aṣọ, ó ti pa dà sí bó ṣe wà tẹ́lẹ̀!
8 Ó sọ pé: “Tí wọn ò bá gbà ọ́ gbọ́, tí wọn ò sì fiyè sí àmì àkọ́kọ́, ó dájú pé wọ́n á gba àmì kejì gbọ́.+
9 Síbẹ̀, tí wọn ò bá gba àmì méjèèjì yìí gbọ́, tí wọn ò sì fetí sí ọ, kí o bu omi díẹ̀ látinú odò Náílì, kí o sì dà á sórí ilẹ̀, omi tí o bù nínú odò Náílì yóò sì di ẹ̀jẹ̀ lórí ilẹ̀.”+
10 Mósè wá sọ fún Jèhófà pé: “Má bínú, Jèhófà, mi ò lè sọ̀rọ̀ dáadáa ṣáájú àkókò yìí àti lẹ́yìn tí o bá ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀, torí ọ̀rọ̀ mi ò já geere,* ahọ́n mi sì wúwo.”+
11 Jèhófà sọ fún un pé: “Ta ló fún èèyàn ní ẹnu, ta ló sì ń mú kó má lè sọ̀rọ̀, kó ya adití, kó ríran kedere tàbí kó fọ́jú? Ǹjẹ́ kì í ṣe èmi Jèhófà ni?
12 Torí náà, lọ, màá wà pẹ̀lú rẹ bí o ṣe ń sọ̀rọ̀,* màá sì kọ́ ọ ní ohun tí o máa sọ.”+
13 Àmọ́ Mósè sọ pé: “Má bínú, Jèhófà, jọ̀ọ́ rán ẹnikẹ́ni tí o bá fẹ́.”
14 Jèhófà wá bínú sí Mósè, ó sì sọ pé: “Áárónì ẹ̀gbọ́n rẹ+ tó jẹ́ ọmọ Léfì ńkọ́? Mo mọ̀ pé ó lè sọ̀rọ̀ dáadáa. Ó sì ti ń bọ̀ wá bá ọ níbí báyìí. Tó bá rí ọ, inú rẹ̀ yóò dùn.+
15 Kí o bá a sọ̀rọ̀, kí o sì fi àwọn ọ̀rọ̀ náà sí ẹnu rẹ̀,+ màá wà pẹ̀lú ẹ̀yin méjèèjì bí o ṣe ń sọ̀rọ̀,+ màá sì kọ́ yín ní ohun tí ẹ máa ṣe.
16 Yóò bá ọ bá àwọn èèyàn náà sọ̀rọ̀, òun ló máa jẹ́ agbẹnusọ fún ọ, ìwọ yóò sì dà bí Ọlọ́run fún un.*+
17 Kí o mú ọ̀pá yìí dání, kí o sì fi ṣe àwọn iṣẹ́ àmì náà.”+
18 Mósè wá pa dà sọ́dọ̀ Jẹ́tírò bàbá ìyàwó rẹ̀,+ ó sì sọ fún un pé: “Jọ̀ọ́, mo fẹ́ pa dà lọ sọ́dọ̀ àwọn arákùnrin mi tó wà ní Íjíbítì kí n lè rí i bóyá wọ́n ṣì wà láàyè.” Jẹ́tírò sọ fún Mósè pé: “Máa lọ ní àlàáfíà.”
19 Lẹ́yìn náà, Jèhófà sọ fún Mósè ní Mídíánì pé: “Pa dà lọ sí Íjíbítì, torí gbogbo àwọn tó fẹ́ pa ọ́* ti kú.”+
20 Mósè wá gbé ìyàwó rẹ̀ àtàwọn ọmọ rẹ̀ sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó forí lé ilẹ̀ Íjíbítì. Mósè sì mú ọ̀pá Ọlọ́run tòótọ́ dání.
21 Jèhófà wá sọ fún Mósè pé: “Tí o bá dé Íjíbítì, rí i pé gbogbo iṣẹ́ ìyanu tí mo fún ọ lágbára láti ṣe lo ṣe níwájú Fáráò.+ Àmọ́, màá jẹ́ kí ọkàn rẹ̀ le,+ kò sì ní jẹ́ kí àwọn èèyàn náà lọ.+
22 Kí o sọ fún Fáráò pé, ‘Ohun tí Jèhófà sọ nìyí: “Ọmọ mi ni Ísírẹ́lì, àkọ́bí mi ni.+
23 Mò ń sọ fún ọ pé, Jẹ́ kí ọmọ mi máa lọ kó lè sìn mí. Àmọ́ tí o ò bá jẹ́ kó lọ, màá pa ọmọkùnrin rẹ, àkọ́bí rẹ.”’”+
24 Lójú ọ̀nà ibi tí wọ́n dé sí, Jèhófà + pàdé rẹ̀, ó sì fẹ́ pa á.+
25 Ni Sípórà+ bá mú akọ òkúta,* ó dádọ̀dọ́* ọmọ rẹ̀, ó sì mú kí adọ̀dọ́ rẹ̀ kan ẹsẹ̀ rẹ̀, ó ní: “Torí ọkọ ẹlẹ́jẹ̀ lo jẹ́ fún mi.”
26 Torí náà, Ó jẹ́ kó lọ. Ìdádọ̀dọ́ náà ló mú kí obìnrin náà pè é ní “ọkọ ẹlẹ́jẹ̀” nígbà yẹn.
27 Jèhófà wá sọ fún Áárónì pé: “Lọ bá Mósè nínú aginjù.”+ Torí náà, ó lọ pàdé rẹ̀ ní òkè Ọlọ́run tòótọ́,+ ó sì fi ẹnu kò ó lẹ́nu láti kí i.
28 Mósè sọ gbogbo ọ̀rọ̀ Jèhófà, ẹni tó rán an, fún Áárónì,+ ó sì sọ fún un nípa gbogbo iṣẹ́ àmì tó pa láṣẹ pé kó ṣe.+
29 Lẹ́yìn náà, Mósè àti Áárónì lọ, wọ́n sì kó gbogbo àgbààgbà àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jọ.+
30 Áárónì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Jèhófà sọ fún Mósè fún wọn, ó sì ṣe àwọn iṣẹ́ àmì náà+ níṣojú àwọn èèyàn náà.
31 Èyí mú kí àwọn èèyàn náà gbà á gbọ́.+ Nígbà tí wọ́n gbọ́ pé Jèhófà ti yíjú sí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì+ àti pé ó ti rí ìyà tó ń jẹ àwọn,+ wọ́n tẹrí ba, wọ́n sì wólẹ̀.
Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
^ Ní Héb., “ẹnu mi wúwo.”
^ Ní Héb., “màá wà pẹ̀lú ẹnu rẹ.”
^ Tàbí “ìwọ yóò jẹ́ àṣojú Ọlọ́run fún un.”
^ Tàbí “àwọn tó ń wá ọkàn rẹ.”
^ Tàbí “ọ̀bẹ tí wọ́n fi òkúta ṣe.”
^ Tàbí “kọlà.”