Sáàmù 95:1-11
95 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a fi ìdùnnú ké jáde sí Jèhófà!+Ẹ jẹ́ kí a kígbe nínú ayọ̀ ìṣẹ́gun sí Àpáta ìgbàlà wa.+
2 Ẹ jẹ́ kí a wá sí iwájú rẹ̀ ti àwa ti ìdúpẹ́;+Ẹ jẹ́ kí a fi àwọn orin atunilára kígbe nínú ayọ̀ ìṣẹ́gun sí i.+
3 Nítorí pé Ọlọ́run ńlá ni Jèhófà+Àti Ọba ńlá lórí gbogbo àwọn ọlọ́run yòókù,+
4 Ẹni tí àwọn ibi jíjinlẹ̀ jù lọ ní ilẹ̀ ayé wà lọ́wọ́ rẹ̀+Àti ẹni tí àwọn téńté òkè ńláńlá jẹ́ tirẹ̀;+
5 Ẹni tí òkun, tí òun fúnra rẹ̀ ṣe, jẹ́ tirẹ̀+Àti ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ ṣẹ̀dá ilẹ̀ gbígbẹ.+
6 Ẹ wọlé wá, ẹ jẹ́ kí a jọ́sìn, kí a sì tẹrí ba;+Ẹ jẹ́ kí a kúnlẹ̀+ níwájú Jèhófà Olùṣẹ̀dá wa.+
7 Nítorí òun ni Ọlọ́run wa, àwa sì ni àwọn ènìyàn pápá ìjẹko rẹ̀ àti àwọn àgùntàn ọwọ́ rẹ̀.+Lónìí, bí ẹ bá fetí sí ohùn rẹ̀,+
8 Ẹ má ṣe sé ọkàn-àyà yín le bí ti Mẹ́ríbà,+Bí ti ọjọ́ Másà ní aginjù,+
9 Nígbà tí àwọn baba ńlá yín dán mi wò;+Wọ́n wádìí mi wò, wọ́n sì rí ìgbòkègbodò mi.+
10 Ogójì ọdún ni mo fi ń bá a nìṣó ní kíkórìíra ìran yẹn tẹ̀gbintẹ̀gbin,+Mo sì tẹ̀ síwájú láti wí pé:“Wọ́n jẹ́ aṣèyówùú nínú ọkàn-àyà,+Àwọn fúnra wọn kò sì wá mọ àwọn ọ̀nà mi”;+
11 Ní ti àwọn tí mo búra nínú ìbínú mi pé:+“Dájúdájú, wọn kì yóò wọ ibi ìsinmi mi.”+

